ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 22:12, 13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Ọba wá pa àṣẹ yìí fún àlùfáà Hilikáyà, Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì, Ákíbórì ọmọ Mikáyà, Ṣáfánì akọ̀wé àti Ásáyà ìránṣẹ́ ọba pé: 13 “Ẹ lọ wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà nítorí tèmi àti nítorí àwọn èèyàn yìí àti nítorí gbogbo Júdà nípa àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé tí a rí yìí; torí ìbínú Jèhófà tó ń jó bí iná lórí wa kò kéré,+ nítorí àwọn baba ńlá wa kò tẹ̀ lé àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí láti ṣe gbogbo ohun tó wà lákọsílẹ̀ fún wa.”

  • Jeremáyà 39:13, 14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Torí náà, Nebusarádánì olórí ẹ̀ṣọ́ àti Nebuṣásíbánì tó jẹ́ Rábúsárísì* àti Nẹgali-ṣárésà tó jẹ́ Rábúmágì* pẹ̀lú gbogbo èèyàn sàràkí-sàràkí ọba Bábílónì ránṣẹ́ 14 pé kí wọ́n mú Jeremáyà jáde kúrò ní Àgbàlá Ẹ̀ṣọ́,+ wọ́n sì fà á lé ọwọ́ Gẹdaláyà+ ọmọ Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì,+ láti mú un wá sí ilé rẹ̀. Torí náà, ó ń gbé ní àárín àwọn èèyàn náà.

  • Jeremáyà 40:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Kí Jeremáyà tó pẹ̀yìn dà, Nebusarádánì sọ pé: “Pa dà sọ́dọ̀ Gẹdaláyà+ ọmọ Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì,+ ẹni tí ọba Bábílónì yàn ṣe olórí àwọn ìlú Júdà, sì máa gbé pẹ̀lú rẹ̀ ní àárín àwọn èèyàn náà tàbí kí o lọ sí ibikíbi tí o bá fẹ́.”

      Olórí ẹ̀ṣọ́ wá fún un ní oúnjẹ díẹ̀ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kó máa lọ.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́