-
Nọ́ńbà 16:39, 40Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
39 Àlùfáà Élíásárì wá kó àwọn ìkóná tí wọ́n fi bàbà ṣe, èyí tí àwọn tó jóná náà mú wá, ó sì fi wọ́n rọ ohun tí wọ́n á fi máa bo pẹpẹ, 40 bí Jèhófà ṣe gbẹnu Mósè sọ fún un. Yóò máa rán àwọn ọmọ Ísírẹ́lì létí pé ẹnikẹ́ni tí kò tọ́ sí,* tí kì í ṣe ọmọ Áárónì kò gbọ́dọ̀ sún mọ́ tòsí láti sun tùràrí níwájú Jèhófà+ àti pé ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ dà bíi Kórà àti àwọn tó ń tì í lẹ́yìn.+
-
-
Ìsíkíẹ́lì 44:15, 16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 “‘Ní ti àwọn ọmọ Léfì tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àwọn ọmọ Sádókù,+ àwọn tó ń bójú tó iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe nínú ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi mí sílẹ̀,+ wọn yóò wá sọ́dọ̀ mi kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ fún mi, wọn yóò sì dúró níwájú mi kí wọ́n lè fi ọ̀rá+ àti ẹ̀jẹ̀ rúbọ sí mi,’+ ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí. 16 ‘Àwọn ni yóò wọnú ibi mímọ́ mi, wọ́n á wá síbi tábìlì mi kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ fún mi,+ wọ́n á sì bójú tó iṣẹ́ tó yẹ kí wọ́n ṣe fún mi.+
-