ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 13:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Màá pe àwọn tó ń gbé ayé lẹ́jọ́ torí ìwà burúkú wọn,+

      Màá sì pe àwọn ẹni burúkú lẹ́jọ́ torí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

      Màá fòpin sí ìyangàn àwọn agbéraga,

      Màá sì rẹ ìgbéraga àwọn oníwà ìkà wálẹ̀.+

  • Jeremáyà 25:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 “‘Ṣùgbọ́n tí àádọ́rin (70) ọdún bá pé,+ màá pe ọba Bábílónì àti orílẹ̀-èdè yẹn wá jíhìn* nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,’+ ni Jèhófà wí, ‘màá sì sọ ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà di ahoro títí láé.+

  • Jeremáyà 27:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ní báyìí, mo ti fi gbogbo ilẹ̀ yìí lé ọwọ́ ìránṣẹ́ mi, Nebukadinésárì+ ọba Bábílónì, kódà mo ti fún un ní àwọn ẹran inú igbó kí wọ́n lè máa sìn ín. 7 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò máa sin òun àti ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ọmọ ọmọ rẹ̀, títí di àkókò tí ìjọba rẹ̀ máa dópin,+ tí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá yóò sì sọ ọ́ di ẹrú wọn.’+

  • Jeremáyà 50:1, 2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 50 Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ nípa Bábílónì,+ nípa ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà, nípasẹ̀ wòlíì Jeremáyà nìyí:

       2 “Ẹ sọ ọ́ láàárín àwọn orílẹ̀-èdè kí ẹ sì kéde rẹ̀.

      Ẹ gbé àmì kan dúró,* ẹ sì kéde rẹ̀.

      Ẹ má fi nǹkan kan pa mọ́!

      Ẹ sọ pé, ‘Wọ́n ti gba Bábílónì.+

      Ìtìjú ti bá Bélì.+

      Méródákì wà nínú ìbẹ̀rù.

      Ìtìjú ti bá àwọn ère rẹ̀.

      Àwọn òrìṣà ẹ̀gbin rẹ̀* wà nínú ìbẹ̀rù.’

  • Jeremáyà 51:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 “Ẹ dán ọfà;+ ẹ gbé àwọn apata ribiti.*

      Jèhófà ti ru ẹ̀mí àwọn ọba Mídíà sókè,+

      Torí ó ní in lọ́kàn láti pa Bábílónì run.

      Nítorí ẹ̀san Jèhófà nìyí, ẹ̀san nítorí tẹ́ńpìlì rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́