5 “Wò ó! ẹranko míì, èkejì, ó dà bíi bíárì.+ A gbé e sókè lẹ́gbẹ̀ẹ́ kan, egungun ìhà mẹ́ta sì wà ní ẹnu rẹ̀ láàárín eyín rẹ̀; a sì sọ fún un pé, ‘Dìde, jẹ ẹran púpọ̀.’+
3 Nígbà tí mo gbé ojú mi sókè, wò ó! àgbò+ kan dúró níwájú ipadò náà, ó sì ní ìwo méjì.+ Ìwo méjèèjì ga, àmọ́ ọ̀kan ga ju ìkejì lọ, èyí tó ga jù sì jáde wá lẹ́yìn náà.+
“Wò ó! Ọba mẹ́ta míì máa dìde fún Páṣíà, ìkẹrin máa kó ọrọ̀ tó pọ̀ jọ ju ti gbogbo àwọn yòókù lọ. Tí ọrọ̀ rẹ̀ bá sì ti mú kó di alágbára, ó máa gbé ohun gbogbo dìde sí ìjọba ilẹ̀ Gíríìsì.+