17 Ọlọ́run tòótọ́ fún àwọn ọ̀dọ́* mẹ́rin yìí ní ìmọ̀ àti òye nínú oríṣiríṣi ìkọ̀wé àti ọgbọ́n; ó sì fún Dáníẹ́lì ní òye láti túmọ̀ onírúurú ìran àti àlá.+
28 Àmọ́ Ọlọ́run kan wà ní ọ̀run, tó jẹ́ Ẹni tó ń ṣí àwọn àṣírí payá,+ ó sì ti jẹ́ kí Ọba Nebukadinésárì mọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ ní apá ìgbẹ̀yìn àwọn ọjọ́. Àlá rẹ nìyí, àwọn ìran tí o sì rí nígbà tí o dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ nìyí: