-
Máàkù 3:16-19Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Àwọn méjìlá (12)+ tó kó jọ* ni Símónì, tó tún pè ní Pétérù,+ 17 Jémíìsì ọmọ Sébédè àti Jòhánù arákùnrin Jémíìsì (ó tún ń pe àwọn yìí ní Bóánágè, tó túmọ̀ sí “Àwọn Ọmọ Ààrá”),+ 18 Áńdérù, Fílípì, Bátólómíù, Mátíù, Tọ́másì, Jémíìsì ọmọ Áfíọ́sì, Tádéọ́sì, Símónì tó jẹ́ Kánánéánì* 19 àti Júdásì Ìsìkáríọ́tù, ẹni tó dà á lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn.
Lẹ́yìn náà, ó wọ inú ilé kan,
-
-
Lúùkù 6:13-16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 Nígbà tí ilẹ̀ mọ́, ó pe àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ sọ́dọ̀, ó sì yan méjìlá (12) lára wọn, ó tún pè wọ́n ní àpọ́sítélì,+ àwọn ni: 14 Símónì, tó tún pè ní Pétérù, Áńdérù arákùnrin rẹ̀, Jémíìsì, Jòhánù, Fílípì,+ Bátólómíù, 15 Mátíù, Tọ́másì,+ Jémíìsì ọmọ Áfíọ́sì, Símónì tí wọ́n ń pè ní “onítara,” 16 Júdásì ọmọ Jémíìsì àti Júdásì Ìsìkáríọ́tù, ẹni tó di ọ̀dàlẹ̀.
-