-
Máàkù 9:2-8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
2 Ọjọ́ mẹ́fà lẹ́yìn náà, Jésù mú Pétérù, Jémíìsì àti Jòhánù dání lọ sí orí òkè kan tó ga fíofío láwọn nìkan. A sì yí i pa dà di ológo níwájú wọn;+ 3 aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tàn yinrin, ó di funfun nini ju bí alágbàfọ̀ èyíkéyìí ní ayé ṣe lè sọ ọ́ di funfun. 4 Bákan náà, Èlíjà àti Mósè fara hàn wọ́n, wọ́n sì ń bá Jésù sọ̀rọ̀. 5 Pétérù wá sọ fún Jésù pé: “Rábì, ó dáa bí a ṣe wà níbí. Torí náà, jẹ́ ká pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fún ọ, ọ̀kan fún Mósè àti ọ̀kan fún Èlíjà.” 6 Ní tòótọ́, kò mọ ohun tí ì bá ṣe, torí ẹ̀rù bà wọ́n gan-an. 7 Ìkùukùu* wá kóra jọ, ó ṣíji bò wọ́n, ohùn kan+ sì dún látinú ìkùukùu náà pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́.+ Ẹ fetí sí i.”+ 8 Lójijì, wọ́n wò yí ká, wọn ò sì rí ẹnì kankan pẹ̀lú wọn mọ́, àfi Jésù nìkan.
-
-
Lúùkù 9:28-36Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
28 Lóòótọ́, ní nǹkan bí ọjọ́ mẹ́jọ lẹ́yìn tó sọ ọ̀rọ̀ yìí, ó mú Pétérù, Jòhánù àti Jémíìsì dání, ó sì gun òkè lọ láti gbàdúrà.+ 29 Bó ṣe ń gbàdúrà, ìrísí ojú rẹ̀ yí pa dà, aṣọ rẹ̀ sì di funfun, ó ń tàn yinrin. 30 Wò ó! ọkùnrin méjì ń bá a sọ̀rọ̀; Mósè àti Èlíjà ni. 31 Àwọn yìí fara hàn nínú ògo, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀ nípa lílọ rẹ̀, èyí tó máa tó mú ṣẹ ní Jerúsálẹ́mù.+ 32 Oorun ń kun Pétérù àti àwọn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ gidigidi, àmọ́ nígbà tí oorun dá lójú wọn, wọ́n rí ògo rẹ̀+ àti ọkùnrin méjì tó dúró pẹ̀lú rẹ̀. 33 Bí àwọn yìí sì ṣe ń kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, Pétérù sọ fún Jésù pé: “Olùkọ́, ó dáa bí a ṣe wà níbí. Torí náà, jẹ́ ká pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fún ọ, ọ̀kan fún Mósè àti ọ̀kan fún Èlíjà.” Kò mọ ohun tó ń sọ. 34 Àmọ́ bó ṣe ń sọ àwọn nǹkan yìí, ìkùukùu* kóra jọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣíji bò wọ́n. Bí wọ́n ṣe wọnú ìkùukùu náà, ẹ̀rù bẹ̀rẹ̀ sí í bà wọ́n. 35 Ohùn kan+ wá dún látinú ìkùukùu náà pé: “Èyí ni Ọmọ mi, ẹni tí mo ti yàn.+ Ẹ fetí sí i.”+ 36 Bí ohùn náà ṣe sọ̀rọ̀, Jésù nìkan ṣoṣo ni wọ́n rí. Àmọ́ wọ́n dákẹ́, wọn ò sì sọ ìkankan nínú àwọn ohun tí wọ́n rí fún ẹnì kankan ní àwọn ọjọ́ yẹn.+
-