-
Máàkù 14:60-65Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
60 Àlùfáà àgbà wá dìde láàárín wọn, ó sì bi Jésù pé: “Ṣé o ò ní fèsì rárá ni? Ẹ̀rí tí àwọn èèyàn yìí ń jẹ́ lòdì sí ọ ńkọ́?”+ 61 Àmọ́ kò sọ̀rọ̀, kò sì fèsì rárá.+ Àlùfáà àgbà tún bẹ̀rẹ̀ sí í bi í ní ìbéèrè, ó sì sọ fún un pé: “Ṣé ìwọ ni Kristi Ọmọ Ẹni Ìbùkún?” 62 Jésù wá sọ pé: “Èmi ni; ẹ sì máa rí Ọmọ èèyàn+ tó jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún agbára,+ tó sì ń bọ̀ pẹ̀lú àwọsánmà* ojú ọ̀run.”+ 63 Ni àlùfáà àgbà bá fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì sọ pé: “Kí la tún fẹ́ fi àwọn ẹlẹ́rìí ṣe?+ 64 Ẹ ti gbọ́ ọ̀rọ̀ òdì náà. Kí lẹ pinnu?”* Gbogbo wọn dá a lẹ́bi pé ikú tọ́ sí i.+ 65 Àwọn kan wá bẹ̀rẹ̀ sí í tutọ́ sí i lára,+ wọ́n sì bo ojú rẹ̀, wọ́n gbá a ní ẹ̀ṣẹ́, wọ́n sì ń sọ fún un pé: “Sọ tẹ́lẹ̀!” Wọ́n gbá a lójú, àwọn òṣìṣẹ́ ilé ẹjọ́ sì mú un.+
-