-
Lúùkù 4:31-37Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
31 Ó wá sọ̀ kalẹ̀ lọ sí Kápánáúmù, ìlú kan ní Gálílì. Ó ń kọ́ wọn ní ọjọ́ Sábáàtì,+ 32 bó ṣe ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ sì yà wọ́n lẹ́nu,+ torí pé ó ń sọ̀rọ̀ tàṣẹtàṣẹ. 33 Ọkùnrin kan wà nínú sínágọ́gù náà tó ní ẹ̀mí kan, ẹ̀mí èṣù àìmọ́, ó sì kígbe pé:+ 34 “Áà! Kí ló pa wá pọ̀, Jésù ará Násárẹ́tì?+ Ṣé o wá pa wá run ni? Mo mọ ẹni tí o jẹ́ gan-an, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run ni ọ́.”+ 35 Àmọ́ Jésù bá a wí, ó ní: “Dákẹ́, kí o sì jáde kúrò nínú rẹ̀.” Torí náà, lẹ́yìn tí ẹ̀mí èṣù náà gbé ọkùnrin náà ṣánlẹ̀ láàárín wọn, ó jáde kúrò nínú rẹ̀ láìṣe é léṣe. 36 Ni ẹnu bá ya gbogbo wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ara wọn pé: “Irú ọ̀rọ̀ wo nìyí? Torí ó ń fi àṣẹ àti agbára lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́, wọ́n sì ń jáde!” 37 Ìròyìn rẹ̀ wá ń tàn káàkiri ṣáá dé gbogbo ìgbèríko tó wà ní àyíká.
-