-
Mátíù 20:29-34Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
29 Bí wọ́n ṣe ń kúrò ní Jẹ́ríkò, èrò rẹpẹtẹ tẹ̀ lé e. 30 Wò ó! àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì tí wọ́n jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà gbọ́ pé Jésù ń kọjá lọ, wọ́n kígbe pé: “Olúwa, ṣàánú wa, Ọmọ Dáfídì!”+ 31 Àmọ́ àwọn èrò náà bá wọn wí, wọ́n ní kí wọ́n dákẹ́; àmọ́ ṣe ni wọ́n tún ń kígbe sókè pé: “Olúwa, ṣàánú wa, Ọmọ Dáfídì!” 32 Torí náà, Jésù dúró, ó pè wọ́n, ó sì sọ pé: “Kí lẹ fẹ́ kí n ṣe fún yín?” 33 Wọ́n sọ fún un pé: “Olúwa, jẹ́ kí ojú wa là.” 34 Àánú wọn ṣe Jésù, ó sì fọwọ́ kan ojú wọn,+ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ wọ́n pa dà ríran, wọ́n sì tẹ̀ lé e.
-
-
Lúùkù 18:35-43Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
35 Bí Jésù ṣe ń sún mọ́ Jẹ́ríkò, ọkùnrin afọ́jú kan jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, ó ń ṣagbe.+ 36 Torí ó gbọ́ ariwo èrò tó ń kọjá lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í wádìí ohun tó ń ṣẹlẹ̀. 37 Wọ́n sọ fún un pé: “Jésù ará Násárẹ́tì ló ń kọjá lọ!” 38 Ló bá kígbe pé: “Jésù, Ọmọ Dáfídì, ṣàánú mi!” 39 Àwọn tó wà níwájú sì bẹ̀rẹ̀ sí í bá a wí, wọ́n ní kó dákẹ́, àmọ́ ṣe ló túbọ̀ ń kígbe pé: “Ọmọ Dáfídì, ṣàánú mi!” 40 Jésù wá dúró, ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú ọkùnrin náà wá sọ́dọ̀ òun. Lẹ́yìn tó sún mọ́ tòsí, Jésù bi í pé: 41 “Kí lo fẹ́ kí n ṣe fún ọ?” Ó sọ pé: “Olúwa, jẹ́ kí n pa dà ríran.” 42 Jésù wá sọ fún un pé: “Kí ojú rẹ pa dà ríran; ìgbàgbọ́ rẹ ti mú ọ lára dá.”+ 43 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó pa dà ríran, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ̀ lé e,+ ó ń yin Ọlọ́run lógo. Bákan náà, gbogbo èèyàn yin Ọlọ́run nígbà tí wọ́n rí èyí.+
-