ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Mátíù 21:1-3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Nígbà tí wọ́n sún mọ́ Jerúsálẹ́mù, tí wọ́n sì dé Bẹtifágè lórí Òkè Ólífì, Jésù rán ọmọ ẹ̀yìn méjì jáde,+ 2 ó sọ fún wọn pé: “Ẹ lọ sínú abúlé ọ̀ọ́kán yìí, gbàrà tí ẹ bá débẹ̀, ẹ máa rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí wọ́n so àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́* tó wà pẹ̀lú rẹ̀. Ẹ tú wọn, kí ẹ sì mú wọn wá fún mi. 3 Tí ẹnì kan bá bá yín sọ ohunkóhun, kí ẹ sọ pé, ‘Olúwa fẹ́ lò wọ́n.’ Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ló máa fi wọ́n ránṣẹ́.”

  • Lúùkù 19:29-34
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 29 Nígbà tó sún mọ́ Bẹtifágè àti Bẹ́tánì, ní òkè tí wọ́n ń pè ní Òkè Ólífì,+ ó rán méjì lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn jáde,+ 30 ó sọ pé: “Ẹ lọ sínú abúlé ọ̀ọ́kán yìí, tí ẹ bá sì ti wọ ibẹ̀, ẹ máa rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́* kan tí wọ́n so, èyí tí èèyàn kankan ò jókòó lé rí. Ẹ tú u, kí ẹ sì mú un wá síbí. 31 Àmọ́ tí ẹnikẹ́ni bá bi yín pé, ‘Kí ló dé tí ẹ fi ń tú u?’ kí ẹ sọ pé, ‘Olúwa fẹ́ lò ó.’” 32 Torí náà, àwọn tó rán níṣẹ́ lọ, wọ́n sì rí i bó ṣe sọ fún wọn gẹ́lẹ́.+ 33 Àmọ́ bí wọ́n ṣe ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn tó ni ín sọ fún wọn pé: “Kí ló dé tí ẹ fi ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yẹn?” 34 Wọ́n sọ pé: “Olúwa fẹ́ lò ó.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́