-
Mátíù 22:23-28Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Lọ́jọ́ yẹn, àwọn Sadusí, tí wọ́n sọ pé kò sí àjíǹde,+ wá bi í pé:+ 24 “Olùkọ́, Mósè sọ pé: ‘Tí ọkùnrin èyíkéyìí bá kú láìní ọmọ, kí arákùnrin rẹ̀ fẹ́ ìyàwó rẹ̀, kó sì bímọ fún arákùnrin rẹ̀.’+ 25 Ó ṣẹlẹ̀ pé arákùnrin méje wà pẹ̀lú wa. Ẹni àkọ́kọ́ fẹ́ ìyàwó, ó sì kú, ó fi ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ fún arákùnrin rẹ̀, nígbà tó jẹ́ pé kò bí ọmọ kankan. 26 Ohun kan náà ló ṣẹlẹ̀ sí ẹnì kejì àti ẹnì kẹta, títí dórí ẹnì keje. 27 Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, obìnrin náà kú. 28 Tí àwọn méjèèje bá wá jíǹde, èwo nínú wọn ló máa fẹ́? Torí gbogbo wọn ni wọ́n ti fi ṣe aya.”
-
-
Lúùkù 20:27-33Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
27 Àmọ́ àwọn kan lára àwọn Sadusí, àwọn tó sọ pé kò sí àjíǹde,+ wá bi í pé:+ 28 “Olùkọ́, Mósè kọ̀wé fún wa pé, ‘Tí arákùnrin ọkùnrin kan bá kú, tó fi ìyàwó sílẹ̀, àmọ́ tí kò bímọ, kí arákùnrin rẹ̀ fẹ́ ìyàwó rẹ̀, kó sì bímọ fún arákùnrin rẹ̀.’+ 29 Ó ṣẹlẹ̀ pé arákùnrin méje wà. Ẹni àkọ́kọ́ fẹ́ ìyàwó, àmọ́ ó kú láìbímọ. 30 Bákan náà ni ẹnì kejì 31 àti ẹnì kẹta náà fẹ́ ẹ. Ohun kan náà ló ṣẹlẹ̀ sí àwọn méjèèje; wọ́n kú láìfi ọmọ kankan sílẹ̀. 32 Níkẹyìn, obìnrin náà kú. 33 Tó bá wá dìgbà àjíǹde, èwo nínú wọn ló máa fẹ́? Torí àwọn méjèèje ló ti fi ṣe aya.”
-