18 Àmọ́ bí wọ́n ṣe bí Jésù Kristi nìyí. Nígbà tí Màríà ìyá rẹ̀ àti Jósẹ́fù ń fẹ́ra wọn sọ́nà, ó ṣẹlẹ̀ pé ó lóyún nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́*+ kí wọ́n tó so wọ́n pọ̀.
20 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn tó fara balẹ̀ ro ọ̀rọ̀ yìí, wò ó! áńgẹ́lì Jèhófà* fara hàn án lójú àlá, ó sọ pé: “Jósẹ́fù, ọmọ Dáfídì, má bẹ̀rù láti mú Màríà ìyàwó rẹ lọ sílé, torí oyún inú rẹ̀* jẹ́ nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́.+