22 “Ẹ̀yin èèyàn Ísírẹ́lì, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí: Jésù ará Násárẹ́tì ni ọkùnrin tí Ọlọ́run fi hàn yín ní gbangba nípasẹ̀ àwọn iṣẹ́ agbára àti àwọn ohun ìyanu* pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ àmì tí Ọlọ́run ṣe nípasẹ̀ rẹ̀ láàárín yín,+ bí ẹ̀yin fúnra yín ṣe mọ̀.
17 Torí ó gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run tó jẹ́ Baba, nígbà tí ògo ọlá ńlá sọ irú ọ̀rọ̀ yìí fún un* pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́ mi, ẹni tí èmi fúnra mi tẹ́wọ́ gbà.”+