6 Aláyọ̀ àti ẹni mímọ́ ni ẹnikẹ́ni tó nípìn-ín nínú àjíǹde àkọ́kọ́;+ ikú kejì+ kò ní àṣẹ lórí wọn,+ àmọ́ wọ́n máa jẹ́ àlùfáà+ Ọlọ́run àti ti Kristi, wọ́n sì máa jọba pẹ̀lú rẹ̀ fún ẹgbẹ̀rún (1,000) ọdún náà.+
8 Àmọ́ ní ti àwọn ojo àti àwọn tí kò ní ìgbàgbọ́+ àti àwọn tí èérí wọn ń ríni lára àti àwọn apààyàn+ àti àwọn oníṣekúṣe*+ àti àwọn tó ń bá ẹ̀mí lò àti àwọn abọ̀rìṣà àti gbogbo òpùrọ́,+ ìpín wọn máa wà nínú adágún tó ń jó, tí a fi imí ọjọ́ sí.+ Èyí túmọ̀ sí ikú kejì.”+