ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 1 Sámúẹ́lì

      • Àpótí náà ní ìpínlẹ̀ àwọn Filísínì (1-12)

        • Dágónì tẹ́ (1-5)

        • Àjàkálẹ̀ àrùn kọ lu àwọn Filísínì (6-12)

1 Sámúẹ́lì 5:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 4:11

1 Sámúẹ́lì 5:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tẹ́ńpìlì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 16:23; 1Kr 10:8-10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/2003, ojú ìwé 25

1 Sámúẹ́lì 5:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 12:12; 1Kr 16:26; Sm 97:7
  • +Ais 46:6, 7

1 Sámúẹ́lì 5:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Dágónì nìkan.”

1 Sámúẹ́lì 5:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìdí yíyọ.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 6:5, 6

1 Sámúẹ́lì 5:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 17:4

1 Sámúẹ́lì 5:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 5:6

1 Sámúẹ́lì 5:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 15:20, 45; 2Ọb 1:2; Emọ 1:8
  • +1Sa 5:7

1 Sámúẹ́lì 5:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 5:6, 9

Àwọn míì

1 Sám. 5:11Sa 4:11
1 Sám. 5:2Ond 16:23; 1Kr 10:8-10
1 Sám. 5:3Ẹk 12:12; 1Kr 16:26; Sm 97:7
1 Sám. 5:3Ais 46:6, 7
1 Sám. 5:61Sa 6:5, 6
1 Sám. 5:81Sa 17:4
1 Sám. 5:91Sa 5:6
1 Sám. 5:10Joṣ 15:20, 45; 2Ọb 1:2; Emọ 1:8
1 Sám. 5:101Sa 5:7
1 Sám. 5:111Sa 5:6, 9
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
1 Sámúẹ́lì 5:1-12

Sámúẹ́lì Kìíní

5 Nígbà tí àwọn Filísínì gba Àpótí+ Ọlọ́run tòótọ́, wọ́n gbé e láti Ẹbinísà wá sí Áṣídódì. 2 Àwọn Filísínì gbé Àpótí Ọlọ́run tòótọ́ wá sínú ilé* Dágónì, wọ́n sì gbé e sẹ́gbẹ̀ẹ́ Dágónì.+ 3 Nígbà tí àwọn ará Áṣídódì dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Dágónì ti ṣubú, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú Àpótí Jèhófà.+ Torí náà, wọ́n gbé Dágónì, wọ́n sì dá a pa dà sí àyè rẹ̀.+ 4 Nígbà tí wọ́n dìde ní àárọ̀ kùtù ọjọ́ tó tẹ̀ lé e, Dágónì tún ti ṣubú, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú Àpótí Jèhófà. Orí Dágónì àti àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ méjèèjì tí gé kúrò, wọ́n sì wà ní ibi àbáwọlé. Ibi tó dà bí ẹja lára rẹ̀ nìkan* ló ṣẹ́ kù. 5 Ìdí nìyẹn tí àwọn àlùfáà Dágónì àti gbogbo àwọn tó ń wọnú ilé Dágónì kì í fi í tẹ ibi àbáwọlé Dágónì ní Áṣídódì títí di òní yìí.

6 Ọwọ́ Jèhófà le mọ́ àwọn ará Áṣídódì, ó kó ìyọnu bá wọn, ó sì ń fi jẹ̀díjẹ̀dí* kọ lu Áṣídódì àti àwọn ìpínlẹ̀ rẹ̀.+ 7 Nígbà tí àwọn èèyàn Áṣídódì rí ohun tó ń ṣẹlẹ̀, wọ́n sọ pé: “Ẹ má ṣe jẹ́ kí Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì máa gbé pẹ̀lú wa, nítorí pé ọwọ́ rẹ̀ ti le mọ́ àwa àti Dágónì ọlọ́run wa.” 8 Nítorí náà, wọ́n ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn alákòóso Filísínì jọ, wọ́n bi wọ́n pé: “Kí ni ká ṣe sí Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì?” Wọ́n fèsì pé: “Ẹ jẹ́ kí a gbé Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì lọ sí Gátì.”+ Torí náà, wọ́n gbé Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì lọ síbẹ̀.

9 Lẹ́yìn tí wọ́n gbé e dé ibẹ̀, ọwọ́ Jèhófà wá sórí ìlú náà, ó sì kó jìnnìjìnnì bá wọn. Ó fìyà jẹ àwọn èèyàn ìlú náà látorí ẹni kékeré dórí ẹni ńlá, jẹ̀díjẹ̀dí sì kọ lù wọ́n.+ 10 Nítorí náà, wọ́n gbé Àpótí Ọlọ́run tòótọ́ ránṣẹ́ sí Ẹ́kírónì,+ àmọ́ gbàrà tí Àpótí Ọlọ́run tòótọ́ dé Ẹ́kírónì, àwọn ará Ẹ́kírónì bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe pé: “Yéè, wọ́n ti gbé Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì wá sọ́dọ̀ wa láti pa àwa àti àwọn èèyàn wa!”+ 11 Nítorí náà, wọ́n ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn alákòóso Filísínì jọ, wọ́n sì sọ pé: “Ẹ gbé Àpótí Ọlọ́run Ísírẹ́lì kúrò lọ́dọ̀ wa, ẹ dá a pa dà sí àyè rẹ̀, kó má bàa pa àwa àti àwọn èèyàn wa.” Nítorí ìbẹ̀rù ikú ti gba gbogbo ìlú náà kan; ọwọ́ Ọlọ́run tòótọ́ sì ti le mọ́ àwọn èèyàn ibẹ̀,+ 12 jẹ̀díjẹ̀dí ti kọ lu àwọn tí kò tíì kú. Igbe ìlú náà fún ìrànlọ́wọ́ sì ti dé ọ̀run.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́