ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sekaráyà 11
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sekaráyà

      • Ohun tó ṣẹlẹ̀ torí wọ́n kọ olùṣọ́ àgùntàn tí Ọlọ́run yàn (1-17)

        • “Bójú tó agbo ẹran tí wọ́n fẹ́ pa” (4)

        • Ọ̀pá méjì: Adùn àti Ìṣọ̀kan (7)

        • Owó iṣẹ́ olùṣọ́ àgùntàn: ọgbọ̀n (30) owó fàdákà (12)

        • Ó sọ owó náà sí ibi ìṣúra (13)

Sekaráyà 11:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “igi óákù.”

Sekaráyà 11:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọmọ kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe (onígọ̀gọ̀).”

Sekaráyà 11:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 34:8

Sekaráyà 11:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 22:25
  • +Ne 5:8
  • +Isk 34:2, 4

Sekaráyà 11:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sek 11:4
  • +Sek 11:10, 14

Sekaráyà 11:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn mi.”

  • *

    Tàbí “ọkàn wọn.”

Sekaráyà 11:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sek 11:7

Sekaráyà 11:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “díwọ̀n.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 26:14, 15; 27:9; Mk 14:10, 11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, ojú ìwé 15

    Ilé Ìṣọ́,

    8/15/2011, ojú ìwé 13

    12/1/2010, ojú ìwé 10

    Ọjọ́ Jèhófà, ojú ìwé 55

Sekaráyà 11:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 21:32
  • +Mt 27:5, 6; Iṣe 1:18

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, ojú ìwé 15

    Ilé Ìṣọ́,

    8/15/2011, ojú ìwé 13

Sekaráyà 11:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sek 11:7
  • +1Ọb 12:19, 20; Isk 37:16

Sekaráyà 11:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 34:2, 4

Sekaráyà 11:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 23:2; Isk 34:6; Mt 9:36
  • +Isk 34:21
  • +Jẹ 31:38
  • +Isk 34:3, 10

Sekaráyà 11:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “di bàìbàì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 23:1; Mt 23:13
  • +Jo 10:12

Àwọn míì

Sek. 11:4Isk 34:8
Sek. 11:5Isk 22:25
Sek. 11:5Ne 5:8
Sek. 11:5Isk 34:2, 4
Sek. 11:7Sek 11:4
Sek. 11:7Sek 11:10, 14
Sek. 11:10Sek 11:7
Sek. 11:12Mt 26:14, 15; 27:9; Mk 14:10, 11
Sek. 11:13Ẹk 21:32
Sek. 11:13Mt 27:5, 6; Iṣe 1:18
Sek. 11:14Sek 11:7
Sek. 11:141Ọb 12:19, 20; Isk 37:16
Sek. 11:15Isk 34:2, 4
Sek. 11:16Jer 23:2; Isk 34:6; Mt 9:36
Sek. 11:16Isk 34:21
Sek. 11:16Jẹ 31:38
Sek. 11:16Isk 34:3, 10
Sek. 11:17Jer 23:1; Mt 23:13
Sek. 11:17Jo 10:12
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Sekaráyà 11:1-17

Sekaráyà

11 “Ṣí àwọn ilẹ̀kùn rẹ, ìwọ Lẹ́bánónì,

Kí iná lè run àwọn igi kédárì rẹ.

 2 Pohùn réré ẹkún, ìwọ igi júnípà, torí igi kédárì ti ṣubú;

Àwọn igi ńláńlá ti pa run!

Ẹ pohùn réré ẹkún, ẹ̀yin igi ràgàjì* ní Báṣánì,

Torí wọ́n ti gé igbó kìjikìji lulẹ̀!

 3 Ẹ fetí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ àgùntàn ń pohùn réré ẹkún,

Torí ògo wọn ti wọmi.

Ẹ fetí sílẹ̀! Àwọn ọmọ kìnnìún* ń ké ramúramù,

Torí igbó tó wà lẹ́bàá Jọ́dánì ti pa run.

4 “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run mi sọ nìyí, ‘Bójú tó agbo ẹran tí wọ́n fẹ́ pa,+ 5 àwọn tó ra àwọn ẹran náà pa wọ́n,+ wọn ò sì dá wọn lẹ́bi. Àwọn tó ń tà wọ́n+ sì sọ pé: “Ẹ yin Jèhófà, torí màá di ọlọ́rọ̀.” Àwọn olùṣọ́ àgùntàn wọn ò sì káàánú wọn.’+

6 “Jèhófà sọ pé, ‘Mi ò ní káàánú àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà mọ́. Torí náà, màá mú kí kálukú kó sí ọwọ́ ọmọnìkejì rẹ̀ àti sí ọwọ́ ọba rẹ̀; wọ́n á pa ilẹ̀ náà run, mi ò sì ní gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ wọn.’”

7 Mo wá bẹ̀rẹ̀ sí í bójú tó agbo ẹran tí wọ́n fẹ́ pa,+ ẹ̀yin tí ìyà ń jẹ nínú agbo ẹran ni mo sì ṣe é fún. Torí náà, mo mú ọ̀pá méjì, mo pe ọ̀kan ní Adùn, mo sì pe èkejì ní Ìṣọ̀kan,+ mo sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe olùṣọ́ àgùntàn agbo ẹran. 8 Ní oṣù kan, mo lé olùṣọ́ àgùntàn mẹ́ta kúrò lẹ́nu iṣẹ́, torí ọ̀rọ̀ wọn sú mi,* àwọn* pẹ̀lú sì kórìíra mi. 9 Mo sì sọ pé: “Mi ò ní ṣe olùṣọ́ àgùntàn yín mọ́. Kí ẹni tó ń kú lọ kú, kí ẹni tó ń ṣègbé lọ sì ṣègbé. Ní ti àwọn tó ṣẹ́ kù, kí wọ́n jẹ ẹran ara wọn.” 10 Torí náà, mo mú ọ̀pá mi tó ń jẹ́ Adùn,+ mo sì kán an, mo sì fagi lé májẹ̀mú mi tí mo bá gbogbo àwọn èèyàn náà dá. 11 Mo fagi lé e lọ́jọ́ yẹn, àwọn tí ìyà ń jẹ nínú agbo ẹran tó ń wò mí sì mọ̀ pé ọ̀rọ̀ Jèhófà ni.

12 Ni mo bá sọ fún wọn pé: “Tó bá dára lójú yín, ẹ fún mi ní owó iṣẹ́; tí kò bá sì dára lójú yín, ẹ mú un dání.” Wọ́n sì san* owó iṣẹ́ mi, ó jẹ́ ọgbọ̀n (30) ẹyọ fàdákà.+

13 Jèhófà wá sọ fún mi pé: “Sọ owó náà sí ibi ìṣúra, iye tó jọjú tí wọ́n rò pé ó tọ́ sí mi.”+ Torí náà, mo mú ọgbọ̀n (30) ẹyọ fàdákà náà, mo sì sọ ọ́ sí ibi ìṣúra ní ilé Jèhófà.+

14 Lẹ́yìn náà, mo kán ọ̀pá mi kejì tó ń jẹ́ Ìṣọ̀kan,+ mo sì ba àjọṣe tó wà láàárín Júdà àti Ísírẹ́lì jẹ́.+

15 Jèhófà sì sọ fún mi pé: “Ó yá, lọ sọ́dọ̀ olùṣọ́ àgùntàn kan tí kò wúlò, kí o sì mú irinṣẹ́ rẹ̀.+ 16 Torí èmi yóò gbé olùṣọ́ àgùntàn kan dìde ní ilẹ̀ náà. Kò ní tọ́jú àwọn àgùntàn tó ń ṣègbé lọ;+ kò ní wá àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn, kò ní tọ́jú àwọn tó fara pa,+ kò sì ní bọ́ àwọn tó lókun láti dúró. Kàkà bẹ́ẹ̀, á jẹ ẹran ara àwọn tó sanra,+ á sì ya pátákò àwọn àgùntàn.+

17 O gbé, ìwọ olùṣọ́ àgùntàn mi tí kò wúlò,+ tó ń pa agbo ẹran tì!+

Idà yóò ṣá a ní apá àti ojú ọ̀tún rẹ̀.

Apá rẹ̀ á rọ pátápátá,

Ojú ọ̀tún rẹ̀ á sì fọ́ yán-án yán-án.”*

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́