Kíróníkà Kejì
27 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni Jótámù+ nígbà tó jọba, ọdún mẹ́rìndínlógún (16) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Jérúṣà ọmọ Sádókù.+ 2 Ó ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Jèhófà bí Ùsáyà bàbá rẹ̀ ti ṣe,+ àmọ́ ní tirẹ̀, kò wọ ibi tí kò yẹ kó wọ̀ nínú tẹ́ńpìlì Jèhófà.+ Síbẹ̀, àwọn èèyàn náà ṣì ń hùwà ibi. 3 Ó kọ́ ẹnubodè apá òkè ilé Jèhófà,+ ó kọ́ ohun púpọ̀ sórí ògiri Ófélì.+ 4 Ó tún kọ́ àwọn ìlú+ sí agbègbè olókè Júdà,+ ó sì kọ́ àwọn ibi olódi+ àti àwọn ilé gogoro+ sí agbègbè onígi. 5 Ó bá ọba àwọn ọmọ Ámónì jà,+ ó sì borí wọn níkẹyìn, tí ó fi jẹ́ pé ní ọdún yẹn, àwọn ọmọ Ámónì fún un ní ọgọ́rùn-ún (100) tálẹ́ńtì* fàdákà àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) òṣùwọ̀n kọ́ọ̀* àlìkámà* àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) ti ọkà bálì. Àwọn ọmọ Ámónì tún san èyí fun un ní ọdún kejì àti ní ọdún kẹta.+ 6 Báyìí ni Jótámù ń lágbára sí i, nítorí ó pinnu* láti máa rìn ní ọ̀nà Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀.
7 Ní ti ìyókù ìtàn Jótámù, gbogbo àwọn ogun tó jà àti àwọn ọ̀nà rẹ̀, ó wà lákọsílẹ̀ nínú Ìwé Àwọn Ọba Ísírẹ́lì àti ti Júdà.+ 8 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni nígbà tó jọba, ọdún mẹ́rìndínlógún (16) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ 9 Níkẹyìn, Jótámù sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀, wọ́n sì sin ín sí Ìlú Dáfídì.+ Áhásì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.+