ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìsíkíẹ́lì 6
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ìsíkíẹ́lì

      • Ọlọ́run yóò bá àwọn òkè Ísírẹ́lì jà (1-14)

        • Ọlọ́run máa rẹ àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wálẹ̀ (4-6)

        • ‘Ẹ ó wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà’ (7)

Ìsíkíẹ́lì 6:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó ṣeé ṣe kí ọ̀rọ̀ Hébérù yìí ní í ṣe pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò fún “ìgbẹ́,” wọ́n sì máa ń lò ó fún ohun tí wọ́n bá kórìíra.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 27:9
  • +Le 26:30

Ìsíkíẹ́lì 6:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 8:1, 2

Ìsíkíẹ́lì 6:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 2:15; 32:29; Mik 3:12
  • +Isk 16:39

Ìsíkíẹ́lì 6:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 14:18
  • +Isk 7:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìjọsìn Mímọ́, ojú ìwé 77

Ìsíkíẹ́lì 6:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 30:10; 44:28; Isk 14:22

Ìsíkíẹ́lì 6:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “oníṣekúṣe; aṣẹ́wó.”

  • *

    Tàbí “mú kí wọ́n bá àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wọn ṣèṣekúṣe.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 30:1, 2; Sm 137:1
  • +Sm 78:40, 41; Ais 63:10
  • +Nọ 15:39
  • +Isk 20:43; 36:31

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìjọsìn Mímọ́, ojú ìwé 98-100

Ìsíkíẹ́lì 6:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 33:29; Da 9:12; Sek 1:6

Ìsíkíẹ́lì 6:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 15:2; 16:4; Isk 5:12

Ìsíkíẹ́lì 6:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 5:13

Ìsíkíẹ́lì 6:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹbọ tí òórùn rẹ̀ ń tuni lára.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 12:15
  • +Jer 8:2
  • +Isk 20:28

Àwọn míì

Ìsík. 6:4Ais 27:9
Ìsík. 6:4Le 26:30
Ìsík. 6:5Jer 8:1, 2
Ìsík. 6:6Jer 2:15; 32:29; Mik 3:12
Ìsík. 6:6Isk 16:39
Ìsík. 6:7Jer 14:18
Ìsík. 6:7Isk 7:4
Ìsík. 6:8Jer 30:10; 44:28; Isk 14:22
Ìsík. 6:9Di 30:1, 2; Sm 137:1
Ìsík. 6:9Sm 78:40, 41; Ais 63:10
Ìsík. 6:9Nọ 15:39
Ìsík. 6:9Isk 20:43; 36:31
Ìsík. 6:10Isk 33:29; Da 9:12; Sek 1:6
Ìsík. 6:11Jer 15:2; 16:4; Isk 5:12
Ìsík. 6:12Isk 5:13
Ìsík. 6:13Isk 12:15
Ìsík. 6:13Jer 8:2
Ìsík. 6:13Isk 20:28
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ìsíkíẹ́lì 6:1-14

Ìsíkíẹ́lì

6 Jèhófà tún sọ fún mi pé: 2 “Ọmọ èèyàn, yíjú sí àwọn òkè Ísírẹ́lì, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sórí wọn. 3 Kí o sọ pé, ‘Ẹ̀yin òkè Ísírẹ́lì, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ: Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ fún àwọn òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, fún àwọn odò àti àwọn àfonífojì nìyí: “Wò ó! Èmi yóò fi idà bá yín jà, èmi yóò sì run àwọn ibi gíga yín. 4 Màá wó àwọn pẹpẹ yín, màá fọ́ àwọn ohun tí ẹ fi ń sun tùràrí,+ màá sì ju òkú àwọn èèyàn yín síwájú àwọn òrìṣà ẹ̀gbin yín.*+ 5 Èmi yóò ju òkú àwọn èèyàn Ísírẹ́lì síwájú àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun yín ká sí àyíká àwọn pẹpẹ yín.+ 6 Ní gbogbo ibi tí ẹ̀ ń gbé, àwọn ìlú yóò di ahoro,+ wọ́n á wó àwọn ibi gíga, yóò sì di ahoro.+ Wọ́n á wó àwọn pẹpẹ yín, wọ́n á sì tú u ká, àwọn òrìṣà ẹ̀gbin yín máa pa run, wọ́n á wó àwọn ohun tí ẹ fi ń sun tùràrí, iṣẹ́ yín á sì pa rẹ́. 7 Òkú á sùn lọ bẹẹrẹbẹ láàárín yín,+ ẹ ó sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà.+

8 “‘“Àmọ́ màá mú kí àwọn kan ṣẹ́ kù, torí àwọn kan lára yín á bọ́ lọ́wọ́ idà àwọn orílẹ̀-èdè nígbà tí ẹ bá fọ́n ká sí àwọn ilẹ̀.+ 9 Àwọn tó bá yè bọ́ yóò rántí mi láàárín àwọn orílẹ̀-èdè tó kó wọn lẹ́rú.+ Wọ́n á rí i pé ó dùn mí gan-an bí ọkàn àìṣòótọ́* wọn ṣe mú kí wọ́n kẹ̀yìn sí mi+ àti bí ojú wọn ṣe mú kí ọkàn wọn fà sí àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wọn.*+ Gbogbo iṣẹ́ ibi àtàwọn ohun ìríra tí wọ́n ti ṣe yóò kó ìtìjú bá wọn, wọ́n á sì kórìíra rẹ̀ gidigidi.+ 10 Wọ́n á sì mọ̀ pé èmi ni Jèhófà àti pé àjálù yìí tí mo sọ pé màá mú bá wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ ẹnu lásán.”’+

11 “Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí: ‘Pàtẹ́wọ́, kí o fẹsẹ̀ kilẹ̀, kí o sì kẹ́dùn torí gbogbo ìwà ibi àti ohun tó ń ríni lára tí ilé Ísírẹ́lì ṣe, torí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀ àrùn ni yóò pa wọ́n.+ 12 Àjàkálẹ̀ àrùn yóò pa ẹni tó wà lọ́nà jíjìn, idà yóò pa ẹni tó wà nítòsí, ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ́ kù, tó sì bọ́ lọ́wọ́ ìwọ̀nyí ni ìyàn yóò pa; bí mo ṣe máa bínú sí wọn gidigidi nìyẹn.+ 13 Ẹ ó sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà,+ nígbà tí òkú wọn bá sùn lọ bẹẹrẹbẹ níbi àwọn òrìṣà ẹ̀gbin wọn, tí àwọn òkú náà yí àwọn pẹpẹ wọn ká,+ lórí gbogbo òkè kékeré àti òkè gíga, lábẹ́ gbogbo igi tó gbẹ̀rẹ̀gẹ̀jigẹ̀ àti lábẹ́ àwọn ẹ̀ka igi ńláńlá tí wọ́n ti rú àwọn ẹbọ olóòórùn dídùn* láti fi wá ojúure gbogbo òrìṣà ẹ̀gbin wọn.+ 14 Èmi yóò na ọwọ́ mi kí n lè fìyà jẹ wọ́n, màá sì sọ ilẹ̀ náà di ahoro, ibi tí wọ́n ń gbé máa di ahoro ju aginjù tó wà nítòsí Díbílà lọ. Wọ́n á sì wá mọ̀ pé èmi ni Jèhófà.’”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́