ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Kíróníkà 24
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 1 Kíróníkà

      • Dáfídì ṣètò àwọn àlùfáà sí àwùjọ 24 (1-19)

      • Àwọn iṣẹ́ míì tí a fún àwọn ọmọ Léfì (20-31)

1 Kíróníkà 24:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 10:1
  • +Ẹk 6:23; 28:1

1 Kíróníkà 24:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 26:61
  • +Nọ 16:39, 40

1 Kíróníkà 24:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:17

1 Kíróníkà 24:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 16:33

1 Kíróníkà 24:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 2:35
  • +2Sa 8:17
  • +2Sa 19:11; 1Ọb 1:5, 7

1 Kíróníkà 24:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Lk 1:5

1 Kíróníkà 24:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 11:9; Lk 1:8, 23

1 Kíróníkà 24:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 23:16; 26:24
  • +Ẹk 6:18

1 Kíróníkà 24:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 23:17

1 Kíróníkà 24:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 23:18

1 Kíróníkà 24:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 26:31

1 Kíróníkà 24:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 46:11

1 Kíróníkà 24:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 23:22

1 Kíróníkà 24:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 16:33

Àwọn míì

1 Kíró. 24:1Le 10:1
1 Kíró. 24:1Ẹk 6:23; 28:1
1 Kíró. 24:2Nọ 26:61
1 Kíró. 24:2Nọ 16:39, 40
1 Kíró. 24:32Sa 8:17
1 Kíró. 24:5Owe 16:33
1 Kíró. 24:61Ọb 2:35
1 Kíró. 24:62Sa 8:17
1 Kíró. 24:62Sa 19:11; 1Ọb 1:5, 7
1 Kíró. 24:10Lk 1:5
1 Kíró. 24:192Ọb 11:9; Lk 1:8, 23
1 Kíró. 24:201Kr 23:16; 26:24
1 Kíró. 24:20Ẹk 6:18
1 Kíró. 24:211Kr 23:17
1 Kíró. 24:221Kr 23:18
1 Kíró. 24:231Kr 26:31
1 Kíró. 24:26Jẹ 46:11
1 Kíró. 24:281Kr 23:22
1 Kíró. 24:31Owe 16:33
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
1 Kíróníkà 24:1-31

Kíróníkà Kìíní

24 Bí a ṣe pín àtọmọdọ́mọ àwọn ọmọ Áárónì nìyí: Àwọn ọmọ Áárónì ni Nádábù, Ábíhù,+ Élíásárì àti Ítámárì.+ 2 Nádábù àti Ábíhù kú ṣáájú bàbá wọn,+ wọn ò sì ní ọmọkùnrin kankan; àmọ́ Élíásárì+ àti Ítámárì ń ṣiṣẹ́ àlùfáà nìṣó. 3 Dáfídì àti Sádókù+ látinú àwọn ọmọ Élíásárì àti Áhímélékì látinú àwọn ọmọ Ítámárì pín wọn sí àwùjọ-àwùjọ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ìsìn wọn. 4 Torí pé olórí tí àwọn ọmọ Élíásárì ní pọ̀ ju ti àwọn ọmọ Ítámárì, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe pín wọn: Àwọn ọmọ Élíásárì ní àwọn mẹ́rìndínlógún (16) tó jẹ́ olórí àwọn agbo ilé bàbá wọn, àwọn ọmọ Ítámárì sì ní àwọn mẹ́jọ tó jẹ́ olórí àwọn agbo ilé bàbá wọn.

5 Síwájú sí i, wọ́n fi kèké pín wọn,+ àwùjọ kan pẹ̀lú àwùjọ kejì, nítorí àwọn olórí ibi mímọ́ àti àwọn olórí ti Ọlọ́run tòótọ́ wá látinú àwọn ọmọ Élíásárì àti àwọn ọmọ Ítámárì. 6 Lẹ́yìn náà, Ṣemáyà ọmọ Nétánélì akọ̀wé àwọn ọmọ Léfì kọ orúkọ wọn sílẹ̀ níwájú ọba àti àwọn ìjòyè àti àlùfáà Sádókù+ àti Áhímélékì+ ọmọ Ábíátárì+ àti àwọn olórí àwọn agbo ilé bàbá àwọn àlùfáà àti ti àwọn ọmọ Léfì, agbo ilé kan ni wọ́n yàn fún Élíásárì, agbo ilé kan ni wọ́n sì yàn fún Ítámárì.

7 Kèké àkọ́kọ́ jáde fún Jèhóáríbù; ìkejì fún Jedáyà, 8 ìkẹta fún Hárímù, ìkẹrin fún Séórímù, 9 ìkarùn-ún fún Málíkíjà, ìkẹfà fún Míjámínì, 10 ìkeje fún Hákósì, ìkẹjọ fún Ábíjà,+ 11 ìkẹsàn-án fún Jéṣúà, ìkẹwàá fún Ṣẹkanáyà, 12 ìkọkànlá fún Élíáṣíbù, ìkejìlá fún Jákímù, 13 ìkẹtàlá fún Húpà, ìkẹrìnlá fún Jéṣébéábù, 14 ìkẹẹ̀ẹ́dógún fún Bílígà, ìkẹrìndínlógún fún Ímérì, 15 ìkẹtàdínlógún fún Hésírì, ìkejìdínlógún fún Hápísésì, 16 ìkọkàndínlógún fún Petaháyà, ogún fún Jéhésíkélì, 17 ìkọkànlélógún fún Jákínì, ìkejìlélógún fún Gámúlì, 18 ìkẹtàlélógún fún Deláyà, ìkẹrìnlélógún fún Maasáyà.

19 Bí a ṣe ṣètò iṣẹ́ tí wọ́n á máa ṣe nínú iṣẹ́ ìsìn+ nígbà tí wọ́n bá wá sínú ilé Jèhófà nìyẹn, gẹ́gẹ́ bí Áárónì baba ńlá wọn ṣe là á kalẹ̀ àti bí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì ṣe pa á láṣẹ fún un.

20 Àwọn ọmọ Léfì tó ṣẹ́ kù nìyí: Ṣúbáélì+ látinú àwọn ọmọ Ámúrámù;+ Jedeáyà látinú àwọn ọmọ Ṣúbáélì; 21 lára Rehabáyà:+ Isiṣáyà tó jẹ́ olórí látinú àwọn ọmọ Rehabáyà; 22 Ṣẹ́lómótì+ látinú àwọn ọmọ Ísárì; Jáhátì látinú àwọn ọmọ Ṣẹ́lómótì; 23 àti látinú àwọn ọmọ Hébúrónì, Jeráyà+ ni olórí, Amaráyà ìkejì, Jáhásíẹ́lì ìkẹta, Jekaméámì ìkẹrin; 24 Míkà látinú àwọn ọmọ Úsíélì; Ṣámírù látinú àwọn ọmọ Míkà. 25 Arákùnrin Míkà ni Isiṣáyà; Sekaráyà sì wá látinú àwọn ọmọ Isiṣáyà.

26 Àwọn ọmọ Mérárì+ ni Máhílì àti Múṣì; Bénò látinú àwọn ọmọ Jaasáyà. 27 Àwọn ọmọ Mérárì nìyí: látọ́dọ̀ Jaasáyà, Bénò, Ṣóhámù, Sákúrì àti Íbírì; 28 látọ̀dọ̀ Máhílì, Élíásárì tí kò ní ọmọkùnrin kankan;+ 29 látọ̀dọ̀ Kíṣì: àwọn ọmọ Kíṣì ni Jéráméélì; 30 àwọn ọmọ Múṣì sì ni Máhílì, Édérì àti Jérímótì.

Àwọn ni àwọn ọmọ Léfì bí wọ́n ṣe wà nínú àwọn agbo ilé bàbá wọn. 31 Àwọn náà tún ṣẹ́ kèké+ bí àwọn ọmọ Áárónì tó jẹ́ arákùnrin wọn ti ṣe níwájú Ọba Dáfídì àti Sádókù àti Áhímélékì àti àwọn olórí àwọn agbo ilé bàbá àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì. Ní ti àwọn agbo ilé bàbá, bí olórí ṣe jẹ́ náà ni àbúrò rẹ̀ ọkùnrin ṣe jẹ́.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́