Orin Sólómọ́nì
7 “Ẹsẹ̀ rẹ mà dára nínú bàtà rẹ o,
Ìwọ ọmọbìnrin tó níwà ọmọlúwàbí!
Àwọn ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ itan rẹ dà bí ohun ọ̀ṣọ́,
Iṣẹ́ ọwọ́ oníṣẹ́ ọnà.
2 Ìdodo rẹ dà bí abọ́ roboto.
Kí àdàlù wáìnì má ṣe tán níbẹ̀.
Ikùn rẹ dà bí òkìtì àlìkámà,*
Tí àwọn òdòdó lílì yí ká.
3 Ọmú rẹ méjèèjì dà bí ọmọ àgbọ̀nrín méjì,
Ó dà bí ọmọ egbin tí wọ́n jẹ́ ìbejì.+
4 Ọrùn rẹ+ dà bí ilé gogoro+ tí wọ́n fi eyín erin kọ́.
Imú rẹ dà bí ilé gogoro Lẹ́bánónì,
Tó dojú kọ Damásíkù.
Irun orí rẹ tó gùn ń dá ọba lọ́rùn.*
6 O mà lẹ́wà o, o mà wuni o,
Ìwọ obìnrin tí mo nífẹ̀ẹ́, o wuni ju gbogbo nǹkan dáradára míì!
8 Mo sọ pé, ‘Màá gun igi ọ̀pẹ lọ,
Kí n lè di àwọn ẹ̀ka tí èso rẹ̀ so mọ́ mú.’
Kí ọmú rẹ dà bí òṣùṣù èso àjàrà,
Kí èémí rẹ máa ta sánsán bí àwọn èso ápù,
9 Kí ẹnu* rẹ sì dà bíi wáìnì tó dára jù.”
“Kó máa lọ tìnrín ní ọ̀fun olólùfẹ́ mi,
Bó ṣe rọra ń ṣàn lórí ètè àwọn tó ń sùn.”
10 Olólùfẹ́ mi ló ni mí,+
Èmi sì ni ọkàn rẹ̀ ń fà sí.
12 Jẹ́ ká tètè jí, ká sì lọ sínú àwọn ọgbà àjàrà,
Ká lọ wò ó bóyá àjàrà ti hù,*
Ibẹ̀ ni màá ti fi ìfẹ́ hàn sí ọ.+
Èyí tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ ká àti èyí tí wọ́n ti ká tẹ́lẹ̀,
Ni mo kó pa mọ́ fún ọ, ìwọ olólùfẹ́ mi.