ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nehemáyà 5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Nehemáyà

      • Nehemáyà fòpin sí ìwà ìrẹ́jẹ (1-13)

      • Nehemáyà kò mọ tara rẹ̀ nìkan (14-19)

Nehemáyà 5:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 15:9

Nehemáyà 5:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọkà.”

Nehemáyà 5:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “owó òde.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:15, 33; Ne 9:36, 37

Nehemáyà 5:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Bí ara àwọn arákùnrin wa ṣe rí ni tiwa náà rí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 21:7; Di 15:12

Nehemáyà 5:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “èlé gọbọi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 22:25; Di 23:19; Sm 15:5; Isk 22:12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2006, ojú ìwé 9

Nehemáyà 5:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:35; Di 15:7, 8; Jer 34:8, 9

Nehemáyà 5:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:36; Ne 5:15

Nehemáyà 5:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 18:5, 8

Nehemáyà 5:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìdá kan nínú ọgọ́rùn-ún,” ìyẹn, lóṣooṣù.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 5:3

Nehemáyà 5:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “gbọn àyà mi dà nù.”

  • *

    Tàbí “Bẹ́ẹ̀ ni kí ó rí!”

Nehemáyà 5:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 10:1
  • +Ne 2:1
  • +Ne 13:6
  • +Ẹsr 8:1
  • +1Kọ 9:14, 15; 2Tẹ 3:8

Nehemáyà 5:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ṣékélì kan jẹ́ gíráàmù 11.4. Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kọ 11:9; 12:14
  • +Ne 5:9

Nehemáyà 5:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Iṣe 20:33; 2Kọ 12:17

Nehemáyà 5:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “adìyẹ.”

  • *

    Tàbí “ni mò ń fún wọn lówó pé kí wọ́n pa fún mi.”

Nehemáyà 5:19

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “fún ire.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ne 13:14; Sm 18:24; Ais 38:3; Mal 3:16

Àwọn míì

Neh. 5:1Di 15:9
Neh. 5:4Di 28:15, 33; Ne 9:36, 37
Neh. 5:5Ẹk 21:7; Di 15:12
Neh. 5:7Ẹk 22:25; Di 23:19; Sm 15:5; Isk 22:12
Neh. 5:8Le 25:35; Di 15:7, 8; Jer 34:8, 9
Neh. 5:9Le 25:36; Ne 5:15
Neh. 5:10Isk 18:5, 8
Neh. 5:11Ne 5:3
Neh. 5:14Ne 10:1
Neh. 5:14Ne 2:1
Neh. 5:14Ne 13:6
Neh. 5:14Ẹsr 8:1
Neh. 5:141Kọ 9:14, 15; 2Tẹ 3:8
Neh. 5:152Kọ 11:9; 12:14
Neh. 5:15Ne 5:9
Neh. 5:16Iṣe 20:33; 2Kọ 12:17
Neh. 5:19Ne 13:14; Sm 18:24; Ais 38:3; Mal 3:16
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Nehemáyà 5:1-19

Nehemáyà

5 Àwọn èèyàn náà àti àwọn ìyàwó wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì ń sunkún nítorí ohun tí àwọn Júù, arákùnrin wọn ń ṣe.+ 2 Àwọn kan ń sọ pé: “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin wa pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀. A gbọ́dọ̀ rí oúnjẹ* tí a máa jẹ, kí a má bàa kú.” 3 Àwọn míì ń sọ pé: “Àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa pẹ̀lú àwọn ilé wa la fi ṣe ohun ìdúró, ká lè rí ọkà lásìkò tí kò sí oúnjẹ.” 4 Àwọn míì sì tún ń sọ pé: “A ti fi àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa yá owó ká lè rí ìṣákọ́lẹ̀* ọba san.+ 5 Ara kan náà àti ẹ̀jẹ̀ kan náà ni àwa àti àwọn arákùnrin wa,* bí àwọn ọmọ wọn ṣe rí náà ni àwọn ọmọ wa rí; síbẹ̀ a ní láti sọ àwọn ọmọkùnrin wa àti àwọn ọmọbìnrin wa di ẹrú, kódà lára àwọn ọmọbìnrin wa ti di ẹrú.+ Àmọ́, a ò ní agbára kankan láti dá èyí dúró, nítorí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa ti di ti àwọn ẹlòmíì.”

6 Inú bí mi gan-an nígbà tí mo gbọ́ igbe ẹkún wọn àti ọ̀rọ̀ yìí. 7 Nítorí náà, mo ro gbogbo rẹ̀ lọ́kàn mi, mo sì bá àwọn èèyàn pàtàkì àti àwọn alábòójútó wí, mo sọ fún wọn pé: “Kálukú yín ń gba èlé* lọ́wọ́ arákùnrin rẹ̀.”+

Yàtọ̀ síyẹn, mo ṣètò àpéjọ ńlá kan nítorí wọn. 8 Mo sọ fún wọn pé: “A ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí wọ́n tà fún àwọn orílẹ̀-èdè pa dà débi tí agbára wa gbé e dé; àmọ́, ṣé ẹ máa wá ta àwọn arákùnrin yín ni,+ ṣé ó yẹ ká tún rà wọ́n pa dà lọ́wọ́ yín ni?” Ni kẹ́kẹ́ bá pa mọ́ wọn lẹ́nu, wọn ò sì rí nǹkan kan sọ. 9 Lẹ́yìn náà, mo sọ pé: “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe yìí kò dára. Ṣé kò yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run wa+ kí àwọn orílẹ̀-èdè, ìyẹn àwọn ọ̀tá wa má bàa pẹ̀gàn wa ni? 10 Yàtọ̀ síyẹn, èmi àti àwọn arákùnrin mi pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ mi ń yá wọn ní owó àti ọkà. Ẹ jọ̀ọ́, ẹ jẹ́ ká jáwọ́ nínú gbígba èlé lórí ohun tí a yáni.+ 11 Ẹ jọ̀ọ́, ẹ dá àwọn nǹkan tí ẹ ti gbà pa dà fún wọn lónìí,+ ìyẹn ilẹ̀ wọn, ọgbà àjàrà wọn, oko ólífì wọn àti ilé wọn, títí kan ìdá ọgọ́rùn-ún* owó, ọkà, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ̀ ń gbà lọ́wọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí èlé.”

12 Wọ́n wá fèsì pé: “A máa dá nǹkan wọ̀nyí pa dà fún wọn, a ò sì ní béèrè ohunkóhun pa dà. A máa ṣe ohun tí o sọ.” Torí náà, mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí wọ́n búra pé wọ́n á mú ìlérí yìí ṣẹ. 13 Mo tún gbọn ibi tó ṣẹ́ po lára aṣọ* mi jáde, mo sì sọ pé: “Ní ọ̀nà yìí, kí Ọlọ́run tòótọ́ gbọn gbogbo ẹni tí kò bá mú ìlérí yìí ṣẹ kúrò nínú ilé rẹ̀ àti kúrò nínú ohun ìní rẹ̀, ọ̀nà yìí sì ni kí a gbà gbọ̀n ọ́n dà nù kí ó sì di òfo.” Gbogbo ìjọ fèsì pé: “Àmín!”* Wọ́n yin Jèhófà, àwọn èèyàn náà sì ṣe ohun tí wọ́n ṣèlérí.

14 Bákan náà, láti ọjọ́ tí ọba ti yàn mí láti di gómìnà wọn+ ní ilẹ̀ Júdà, láti ogún ọdún+ sí ọdún kejìlélọ́gbọ̀n+ Ọba Atasásítà,+ ó jẹ́ ọdún méjìlá (12), èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ tó yẹ gómìnà.+ 15 Àmọ́, àwọn gómìnà tó wà ṣáájú mi ti di ẹrù tó wúwo sórí àwọn èèyàn náà, wọ́n sì ń gba ogójì (40) ṣékélì* fàdákà lọ́wọ́ wọn fún oúnjẹ àti wáìnì lójoojúmọ́. Àwọn ìránṣẹ́ wọn tún ń ni àwọn èèyàn lára. Ṣùgbọ́n mi ò ṣe bẹ́ẹ̀+ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run.+

16 Yàtọ̀ síyẹn, mo ṣe nínú iṣẹ́ ògiri yìí, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi kóra jọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà, a kò sì gba ilẹ̀ kankan.+ 17 Àádọ́jọ (150) Júù àti àwọn alábòójútó ló ń jẹun lórí tábìlì mi, títí kan àwọn tó wá sọ́dọ̀ wa látinú àwọn orílẹ̀-èdè. 18 Lójoojúmọ́, akọ màlúù kan, àgùntàn mẹ́fà tó dáa àti àwọn ẹyẹ* ni wọ́n ń pa fún mi,* a sì máa ń pèsè ọ̀pọ̀ wáìnì lóríṣiríṣi lẹ́ẹ̀kan lọ́jọ́ mẹ́wàá. Síbẹ̀, mi ò béèrè oúnjẹ tó yẹ gómìnà, nítorí pé iṣẹ́ tó wà lọ́rùn àwọn èèyàn náà pọ̀, ó sì ti wọ̀ wọ́n lọ́rùn. 19 Ọlọ́run mi, jọ̀wọ́ rántí mi sí rere* lórí gbogbo ohun tí mo ti ṣe nítorí àwọn èèyàn yìí.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́