Sámúẹ́lì Kìíní
27 Àmọ́ Dáfídì sọ nínú ọkàn rẹ̀ pé: “Lọ́jọ́ kan, Sọ́ọ̀lù máa pa mí. Ohun tó máa dáa jù ni pé kí n sá lọ+ sí ilẹ̀ àwọn Filísínì; ìgbà yẹn ni Sọ́ọ̀lù á jáwọ́ nínú wíwá mi kiri ní gbogbo ìpínlẹ̀ Ísírẹ́lì,+ màá sì bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.” 2 Ni Dáfídì àti ọgọ́rùn-ún mẹ́fà (600) ọkùnrin+ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ bá gbéra, wọ́n sì lọ sọ́dọ̀ Ákíṣì+ ọmọ Máókì, ọba Gátì. 3 Dáfídì dúró sọ́dọ̀ Ákíṣì ní Gátì, òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀, kálukú pẹ̀lú agbo ilé rẹ̀. Àwọn ìyàwó Dáfídì méjèèjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀, Áhínóámù+ ará Jésírẹ́lì àti Ábígẹ́lì,+ opó Nábálì, ará Kámẹ́lì. 4 Nígbà tí wọ́n sọ fún Sọ́ọ̀lù pé Dáfídì ti sá lọ sí Gátì, kò tún wá a kiri mọ́.+
5 Nígbà náà, Dáfídì sọ fún Ákíṣì pé: “Tí mo bá rí ojú rere rẹ, jẹ́ kí wọ́n fún mi ní àyè nínú ọ̀kan lára àwọn ìlú tó wà ní ìgbèríko, kí n lè máa gbé ibẹ̀. Kí nìdí tí ìránṣẹ́ rẹ á fi máa bá ọ gbé nínú ìlú ọba?” 6 Torí náà, Ákíṣì fún un ní Síkílágì+ ní ọjọ́ yẹn. Ìdí nìyẹn tí Síkílágì fi jẹ́ ti àwọn ọba Júdà títí di òní yìí.
7 Àkókò* tí Dáfídì fi gbé ní ìgbèríko àwọn Filísínì jẹ́ ọdún kan àti oṣù mẹ́rin.+ 8 Dáfídì máa ń jáde lọ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ̀ kí wọ́n lè kó nǹkan àwọn ará Géṣúrì+ àti àwọn Gísì àti àwọn ọmọ Ámálékì,+ nítorí wọ́n ń gbé ilẹ̀ tí ó lọ láti Télámù títí dé Ṣúrì+ àti títí dé ilẹ̀ Íjíbítì. 9 Nígbà tí Dáfídì bá lọ gbéjà ko ilẹ̀ náà, kì í dá ọkùnrin tàbí obìnrin sí,+ àmọ́ á kó àwọn agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti ràkúnmí àti aṣọ, lẹ́yìn náà, á wá pa dà sọ́dọ̀ Ákíṣì. 10 Ákíṣì á béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Ibo ni ẹ ti lọ kó nǹkan lónìí?” Dáfídì á dáhùn pé: “Apá gúúsù* Júdà”+ tàbí “Apá gúúsù àwọn ọmọ Jéráméélì”+ tàbí “Apá gúúsù àwọn Kénì”+ ni. 11 Dáfídì kì í dá ọkùnrin tàbí obìnrin kankan sí tó máa mú wá sí Gátì, á sọ pé: “Kí wọ́n má bàa rojọ́ wa fún wọn pé, ‘Ohun tí Dáfídì ṣe nìyí.’” (Bí ó sì ṣe máa ń ṣe nìyẹn ní gbogbo ìgbà tó fi ń gbé ní ìgbèríko àwọn Filísínì.) 12 Nítorí náà, Ákíṣì gba Dáfídì gbọ́, ó sì ń sọ fún ara rẹ̀ pé: ‘Ó dájú pé ó ti di ẹni ìkórìíra láàárín àwọn èèyàn rẹ̀ Ísírẹ́lì, torí náà, á máa jẹ́ ìránṣẹ́ mi títí lọ.’