ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 17
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Jèhóṣáfátì di ọba Júdà (1-6)

      • Wọ́n ń kọ́ àwọn èèyàn káàkiri (7-9)

      • Ẹgbẹ́ ológun Jèhóṣáfátì (10-19)

2 Kíróníkà 17:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 15:24; 22:41

2 Kíróníkà 17:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 15:8

2 Kíróníkà 17:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 8:15

2 Kíróníkà 17:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ó rìn nínú àṣẹ rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:29; 2Kr 26:1, 5
  • +1Ọb 12:28-30; 13:33

2 Kíróníkà 17:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 9:4, 5; Sm 132:12
  • +2Kr 18:1

2 Kíróníkà 17:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 22:42, 43
  • +Di 7:5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    6/15/2009, ojú ìwé 12

2 Kíróníkà 17:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 33:8, 10; Mal 2:7

2 Kíróníkà 17:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:11; Joṣ 1:7, 8; Ne 8:7

2 Kíróníkà 17:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “owó òde.”

2 Kíróníkà 17:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 18:1
  • +2Kr 14:2, 6
  • +1Ọb 9:19; 2Kr 8:3, 4

2 Kíróníkà 17:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 13:3; 26:11-13

2 Kíróníkà 17:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọrun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 49:27
  • +2Kr 14:8

2 Kíróníkà 17:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 11:5, 23

Àwọn míì

2 Kíró. 17:11Ọb 15:24; 22:41
2 Kíró. 17:22Kr 15:8
2 Kíró. 17:32Sa 8:15
2 Kíró. 17:4Di 4:29; 2Kr 26:1, 5
2 Kíró. 17:41Ọb 12:28-30; 13:33
2 Kíró. 17:51Ọb 9:4, 5; Sm 132:12
2 Kíró. 17:52Kr 18:1
2 Kíró. 17:61Ọb 22:42, 43
2 Kíró. 17:6Di 7:5
2 Kíró. 17:8Di 33:8, 10; Mal 2:7
2 Kíró. 17:9Di 31:11; Joṣ 1:7, 8; Ne 8:7
2 Kíró. 17:122Kr 18:1
2 Kíró. 17:122Kr 14:2, 6
2 Kíró. 17:121Ọb 9:19; 2Kr 8:3, 4
2 Kíró. 17:142Kr 13:3; 26:11-13
2 Kíró. 17:17Jẹ 49:27
2 Kíró. 17:172Kr 14:8
2 Kíró. 17:192Kr 11:5, 23
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 17:1-19

Kíróníkà Kejì

17 Jèhóṣáfátì ọmọ rẹ̀ + jọba ní ipò rẹ̀, ó sì mú kí ipò rẹ̀ fìdí múlẹ̀ lórí Ísírẹ́lì. 2 Ó kó àwọn ológun sí gbogbo ìlú olódi Júdà, ó sì fi àwọn ọmọ ogun sí ilẹ̀ Júdà àti sínú àwọn ìlú Éfúrémù tí Ásà bàbá rẹ̀ gbà.+ 3 Jèhófà wà pẹ̀lú Jèhóṣáfátì nítorí pé ó rìn ní àwọn ọ̀nà tí Dáfídì+ baba ńlá rẹ̀ rìn nígbà àtijọ́, kò sì wá àwọn Báálì. 4 Ó wá Ọlọ́run bàbá rẹ̀,+ ó ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́,* kò sì hu ìwà tí Ísírẹ́lì ń hù.+ 5 Jèhófà fìdí ìjọba náà múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀;+ gbogbo Júdà ń mú ẹ̀bùn wá fún Jèhóṣáfátì, ó sì ní ọrọ̀ àti ògo tó pọ̀ gan-an.+ 6 Ó ní ìgboyà láti máa rìn ní àwọn ọ̀nà Jèhófà, kódà ó mú àwọn ibi gíga+ àti àwọn òpó òrìṣà*+ kúrò ní Júdà.

7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó ránṣẹ́ pe àwọn ìjòyè rẹ̀, ìyẹn Bẹni-háílì, Ọbadáyà, Sekaráyà, Nétánélì àti Mikáyà, ó ní kí wọ́n lọ máa kọ́ni ní àwọn ìlú Júdà. 8 Àwọn ọmọ Léfì wà pẹ̀lú wọn, àwọn ni: Ṣemáyà, Netanáyà, Sebadáyà, Ásáhélì, Ṣẹ́mírámótì, Jèhónátánì, Ádóníjà, Tóbíjà àti Tobu-ádóníjà, àwọn àlùfáà+ tó wà pẹ̀lú wọn ni Élíṣámà àti Jèhórámù. 9 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ni ní Júdà, wọ́n mú ìwé Òfin Jèhófà dání,+ wọ́n sì lọ yí ká gbogbo àwọn ìlú Júdà, wọ́n ń kọ́ àwọn èèyàn.

10 Ẹ̀rù Jèhófà ba gbogbo ìjọba àwọn ilẹ̀ tó yí Júdà ká, wọn ò sì bá Jèhóṣáfátì jà. 11 Àwọn Filísínì ń mú ẹ̀bùn àti owó wá fún Jèhóṣáfátì, wọ́n fi ń san ìṣákọ́lẹ̀.* Àwọn ará Arébíà mú ẹgbẹ̀rún méje ó lé ọgọ́rùn-ún méje (7,700) àgbò àti ẹgbẹ̀rún méje ó lé ọgọ́rùn-ún méje (7,700) òbúkọ wá fún un látinú agbo ẹran wọn.

12 Agbára Jèhóṣáfátì ń pọ̀ sí i,+ ó sì ń kọ́ àwọn ibi olódi+ àti àwọn ìlú tó ń kó nǹkan pa mọ́ sí+ ní Júdà. 13 Ó gbé ọ̀pọ̀ nǹkan ṣe ní àwọn ìlú Júdà, ó sì ní àwọn ọmọ ogun, àwọn jagunjagun tó lákíkanjú, ní Jerúsálẹ́mù. 14 Wọ́n pín wọn sí agbo ilé àwọn bàbá wọn: nínú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún látinú Júdà, àkọ́kọ́ ni Ádínáhì olórí, ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (300,000) jagunjagun tó lákíkanjú sì wà pẹ̀lú rẹ̀.+ 15 Ẹni tó wà lábẹ́ àṣẹ rẹ̀ ni Jèhóhánánì olórí, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá (280,000) sì wà pẹ̀lú rẹ̀. 16 Ẹni tó tún wà lábẹ́ àṣẹ rẹ̀ ni Amasáyà ọmọ Síkírì, ó yọ̀ǹda ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, ọ̀kẹ́ mẹ́wàá (200,000) jagunjagun tó lákíkanjú sì wà pẹ̀lú rẹ̀. 17 Bákan náà, Élíádà látinú Bẹ́ńjámínì,+ ó jẹ́ jagunjagun tó lákíkanjú, ọ̀kẹ́ mẹ́wàá (200,000) ọkùnrin tí wọ́n ní ọfà* lọ́wọ́, tí wọ́n sì gbé apata dání wà pẹ̀lú rẹ̀.+ 18 Ẹni tó tún wà lábẹ́ àṣẹ rẹ̀ ni Jèhósábádì, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án (180,000) ọkùnrin tí wọ́n ti gbára dì láti wọṣẹ́ ológun sì wà pẹ̀lú rẹ̀. 19 Gbogbo wọn ló ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba, yàtọ̀ sí àwọn tí ọba fi sínú àwọn ìlú olódi ní gbogbo Júdà.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́