ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Wọ́n dádọ̀dọ́ ní Gílígálì (1-9)

      • Wọ́n ṣe Ìrékọjá; mánà ò rọ̀ mọ́ (10-12)

      • Olórí àwọn ọmọ ogun Jèhófà (13-15)

Jóṣúà 5:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “lápá ibi tí òkun wà ní.”

  • *

    Tàbí “ìpayà bá wọn.”

  • *

    Ní Héb., “kò sì sí ẹ̀mí kankan mọ́ nínú wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 10:15, 16
  • +Nọ 13:29
  • +Ẹk 15:15; Joṣ 2:24
  • +Joṣ 2:9-11

Jóṣúà 5:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kọlà fún.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 17:9-11

Jóṣúà 5:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó túmọ̀ sí “Òkè Adọ̀dọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 5:8, 9

Jóṣúà 5:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn ọkùnrin tó dàgbà tó láti jagun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:29; 26:65; Di 2:14

Jóṣúà 5:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:33; Di 1:3
  • +Nọ 14:22, 23
  • +Di 1:35
  • +Jẹ 13:14, 15; Ẹk 33:1
  • +Ẹk 3:8; Nọ 13:26, 27; Isk 20:6

Jóṣúà 5:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:31

Jóṣúà 5:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó túmọ̀ sí “Yí; Yí Kúrò.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 4:19; 5:3

Jóṣúà 5:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 12:24, 25; Nọ 9:5

Jóṣúà 5:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 12:18

Jóṣúà 5:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:35
  • +Di 6:10-12; 8:10

Jóṣúà 5:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 18:2; Ond 13:6; Iṣe 1:10
  • +Ẹk 23:23; Nọ 22:23; 1Kr 21:16

Jóṣúà 5:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “balógun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:20; 1Ọb 22:19; Da 10:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    10/2018, ojú ìwé 23

    Ilé Ìṣọ́,

    12/1/2004, ojú ìwé 9

    6/15/1998, ojú ìwé 24

Jóṣúà 5:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 3:4, 5

Àwọn míì

Jóṣ. 5:1Jẹ 10:15, 16
Jóṣ. 5:1Nọ 13:29
Jóṣ. 5:1Ẹk 15:15; Joṣ 2:24
Jóṣ. 5:1Joṣ 2:9-11
Jóṣ. 5:2Jẹ 17:9-11
Jóṣ. 5:3Joṣ 5:8, 9
Jóṣ. 5:4Nọ 14:29; 26:65; Di 2:14
Jóṣ. 5:6Nọ 14:33; Di 1:3
Jóṣ. 5:6Nọ 14:22, 23
Jóṣ. 5:6Di 1:35
Jóṣ. 5:6Jẹ 13:14, 15; Ẹk 33:1
Jóṣ. 5:6Ẹk 3:8; Nọ 13:26, 27; Isk 20:6
Jóṣ. 5:7Nọ 14:31
Jóṣ. 5:9Joṣ 4:19; 5:3
Jóṣ. 5:10Ẹk 12:24, 25; Nọ 9:5
Jóṣ. 5:11Ẹk 12:18
Jóṣ. 5:12Ẹk 16:35
Jóṣ. 5:12Di 6:10-12; 8:10
Jóṣ. 5:13Jẹ 18:2; Ond 13:6; Iṣe 1:10
Jóṣ. 5:13Ẹk 23:23; Nọ 22:23; 1Kr 21:16
Jóṣ. 5:14Ẹk 23:20; 1Ọb 22:19; Da 10:13
Jóṣ. 5:15Ẹk 3:4, 5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 5:1-15

Jóṣúà

5 Gbàrà tí gbogbo ọba àwọn Ámórì,+ tí wọ́n wà lápá ìwọ̀ oòrùn* Jọ́dánì àti gbogbo ọba àwọn ọmọ Kénáánì,+ tí wọ́n wà létí òkun gbọ́ pé Jèhófà ti mú kí omi Jọ́dánì gbẹ níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì títí wọ́n fi sọdá, ọkàn wọn domi,*+ kò sì sí ẹni tó ní ìgboyà mọ́* torí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+

2 Ìgbà yẹn ni Jèhófà sọ fún Jóṣúà pé: “Fi akọ òkúta ṣe àwọn ọ̀bẹ fún ara rẹ, kí o sì tún dádọ̀dọ́*+ àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì lẹ́ẹ̀kejì.” 3 Jóṣúà wá fi akọ òkúta ṣe àwọn ọ̀bẹ, ó sì dádọ̀dọ́ àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì ní Gibeati-háárálótì.*+ 4 Ìdí tí Jóṣúà fi dádọ̀dọ́ wọn ni pé: Gbogbo ọkùnrin tó wà nínú àwọn èèyàn náà, tí wọ́n kúrò ní Íjíbítì, gbogbo ọkùnrin ogun,* ti kú sínú aginjù lẹ́nu ìrìn àjò wọn lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Íjíbítì.+ 5 Gbogbo àwọn tó kúrò ní Íjíbítì ló dádọ̀dọ́, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí wọ́n bí ní aginjù lẹ́nu ìrìn àjò wọn lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Íjíbítì kò tíì dádọ̀dọ́. 6 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti fi ogójì (40) ọdún+ rìn ní aginjù, títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi kú, ìyẹn àwọn ọkùnrin ogun tó kúrò ní Íjíbítì, tí wọn ò fetí sí ohùn Jèhófà.+ Jèhófà búra fún wọn pé òun kò ní jẹ́ kí wọ́n rí ilẹ̀+ tí Jèhófà búra fún àwọn baba ńlá wọn pé òun máa fún wa,+ ilẹ̀ tí wàrà àti oyin ti ń ṣàn.+ 7 Ó fi àwọn ọmọ wọn rọ́pò wọn.+ Àwọn yìí ni Jóṣúà dádọ̀dọ́ wọn; aláìdádọ̀dọ́ ni wọ́n torí pé wọn ò tíì dádọ̀dọ́ lẹ́nu ìrìn àjò wọn.

8 Nígbà tí wọ́n dádọ̀dọ́ gbogbo orílẹ̀-èdè náà tán, wọ́n dúró síbi tí wọ́n pàgọ́ sí títí ara wọn fi jinná.

9 Jèhófà wá sọ fún Jóṣúà pé: “Mo yí ẹ̀gàn Íjíbítì kúrò lórí yín lónìí.” Wọ́n wá ń pe ibẹ̀ ní Gílígálì*+ títí di òní yìí.

10 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣì dúró sí Gílígálì tí wọ́n pàgọ́ sí, wọ́n ṣe Ìrékọjá ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù,+ ní aṣálẹ̀ tó tẹ́jú ní Jẹ́ríkò. 11 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ èso ilẹ̀ náà ní ọjọ́ tó tẹ̀ lé Ìrékọjá, wọ́n jẹ búrẹ́dì aláìwú+ àti àyangbẹ ọkà lọ́jọ́ yẹn kan náà. 12 Mánà ò rọ̀ fún wọn ní ọjọ́ tó tẹ̀ lé ọjọ́ tí wọ́n jẹ lára èso ilẹ̀ náà; àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò rí mánà kó mọ́,+ wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ èso ilẹ̀ Kénáánì ní ọdún yẹn.+

13 Nígbà tí Jóṣúà wà nítòsí Jẹ́ríkò, ó gbójú sókè, ó sì rí ọkùnrin kan+ tó dúró níwájú rẹ̀, tó fa idà yọ.+ Jóṣúà lọ bá a, ó sì bi í pé: “Ṣé tiwa lò ń ṣe ni, àbí tàwọn ọ̀tá wa?” 14 Ó fèsì pé: “Rárá o, mo wá gẹ́gẹ́ bí olórí* àwọn ọmọ ogun Jèhófà.”+ Ni Jóṣúà bá dojú bolẹ̀, ó sì wólẹ̀, ó sọ fún un pé: “Kí ni olúwa mi fẹ́ sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?” 15 Olórí àwọn ọmọ ogun Jèhófà wá sọ fún Jóṣúà pé: “Bọ́ bàtà ẹsẹ̀ rẹ, torí ilẹ̀ mímọ́ ni ibi tí o dúró sí.” Jóṣúà sì ṣe bẹ́ẹ̀ lójú ẹsẹ̀.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́