ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g97 10/22 ojú ìwé 31
  • Kí Ní Ń Mú Àwọn Ènìyàn Láyọ̀?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ní Ń Mú Àwọn Ènìyàn Láyọ̀?
  • Jí!—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bí A Ṣe Lè Láyọ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Ayọ Tootọ Ninu Ṣiṣiṣẹsin Jehofa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
  • Àwọn Èèyàn Ń Wá Ohun Tó Máa Fún Wọn Láyọ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
  • Aláyọ̀ Ni Àwọn Tó Ń Sin “Ọlọ́run Aláyọ̀”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
Àwọn Míì
Jí!—1997
g97 10/22 ojú ìwé 31

Kí Ní Ń Mú Àwọn Ènìyàn Láyọ̀?

Ó ti pé ẹ̀wádún méjì tí àwùjọ àwọn olùṣèwádìí jákèjádò ayé kan ti ń ṣe ìwádìí àfẹ̀sọ̀ṣe kan nípa ayọ̀. Kí ni wọ́n rí? Ìwé ìròyìn Scientific American sọ pé: “Ó jọ pé kì í ṣe àwọn ipò òde ara ní ń fa ayọ̀ tó bẹ́ẹ̀.”

Ìwé ìròyìn nípa ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì yí tún sọ pé: “Bákan náà, ọrọ̀ kọ́ ní ń pinnu ayọ̀. Àwọn ènìyàn kò láyọ̀ sí i láàárín àkókò tí búrùjí àwọn àṣà ìṣẹ̀dálẹ̀ wọn ń pọ̀ sí i. . . . Ní ọ̀pọ̀ jù lọ orílẹ̀-èdè, ìbátan tí ó wà láàárín owó tí ń wọlé àti ayọ̀ kò tó nǹkan.”

Àwọn ìwádìí náà fi àwọn ìtẹ̀sí mẹ́rin hàn tí ó jẹ́ ànímọ́ àwọn tí wọ́n láyọ̀: Wọ́n fẹ́ràn ara wọn, wọ́n sì ní ọ̀wọ̀ ara ẹni gan-an; wọ́n lérò pé àwọn ní àkóso lórí ìgbésí ayé ara ẹni wọn; wọ́n máa ń wọ̀nà fún rere; wọ́n sì ń túra ká sí àwọn ẹlòmíràn. Ní àfikún, ìgbéyàwó tó já sí rere àti ipò ìbátan tímọ́tímọ́ ń mú kí ìgbésí ayé jẹ́ aláyọ̀, ó sì jọ pé ìwọ̀nyí ń mú kí ipò ìlera àti ẹ̀mí gígùn pọ̀ sí i.

Lọ́nà tó gbàfiyèsí, ìwé ìròyìn Scientific American sọ pé: “Àwọn ènìyàn tí ń ṣe dáradára ní ti ìsìn tún ròyìn níní ayọ̀ púpọ̀. Ìwádìí kan tí a ṣe lórí èrò aráàlú ṣàwárí pé ó ṣeé ṣe kí àwọn ènìyàn tí wọ́n lẹ́mìí ìsìn gan-an sọ pé àwọn láyọ̀ ní ìlọ́po méjì ti àwọn tí kò fi bẹ́ẹ̀ fara fún ìsìn. Àwọn ìwádìí mìíràn, títí kan ìwádìí kan tí àwọn orílẹ̀-èdè 16 kan pawọ́ pọ̀ ṣe ní lílo 166,000 ènìyàn ní orílẹ̀-èdè 14, fi hàn pé ayọ̀ àti ìtẹ́lọ́rùn tí a ròyìn pé àwọn kan ń ní nínú ìgbésí ayé ń pọ̀ sí i nígbà tí wọ́n bá ń dara pọ̀ mọ́ ìsìn, tí wọ́n sì ń lọ síbi ìjọsìn déédéé.”

Tipẹ́tipẹ́ sẹ́yìn ni onísáàmù náà, Dáfídì, ti fi hàn pé ayọ̀ ẹnì kan ní ìsopọ̀ tímọ́tímọ́ pẹ̀lú ìjọsìn oníṣọ̀kan ti Jèhófà Ọlọ́run, ní kíkọ̀wé pé: “Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé, Ẹ jẹ́ kí a lọ sí ilé Olúwa.”—Orin Dáfídì 122:1.

Abájọ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi rọ àwọn Kristẹni ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ pé: “Ẹ . . . jẹ́ kí a gba ti ara wa rò lẹ́nì kíní kejì láti ru ara wa lọ́kàn sókè sí ìfẹ́ àti sí àwọn iṣẹ́ àtàtà, kí a má máa ṣá ìpéjọpọ̀ ara wa tì”! (Hébérù 10:24, 25) Ní tòótọ́, pípéjọ láti jọ́sìn Ọlọ́run pẹ̀lú àwọn tí wọ́n ní irú ìgbàgbọ́ ṣíṣeyebíye kan náà jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ aláyọ̀ fún àwọn olùfẹ́ òtítọ́ Bíbélì. Àràádọ́ta ọ̀kẹ́ Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tí rí i pé èyí jẹ́ òtítọ́, wọ́n sì ń ké sí ọ láti wá rí èyí fúnra rẹ nípa dídara pọ̀ mọ́ wọn nínú ìjọsìn ní Gbọ̀ngàn Ìjọba tí ó sún mọ́ ọ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́