ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 7/11 ojú ìwé 19
  • Ǹjẹ́ Ètè Rẹ Jẹ́ “Ohun Èlò Tí ó Ṣeyebíye”?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Ètè Rẹ Jẹ́ “Ohun Èlò Tí ó Ṣeyebíye”?
  • Jí!—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ‘Ètè Òtítọ́ Yóò Dúró Títí Láé’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Máa Rìn Ní ‘Ipa Ọ̀nà Ìdúróṣánṣán’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • ‘Ìbùkún Wà Fún Olódodo’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • “Ọgbọ́n Jẹ́ Fún Ìdáàbòbò”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
Àwọn Míì
Jí!—2011
g 7/11 ojú ìwé 19

Ǹjẹ́ Ètè Rẹ Jẹ́ “Ohun Èlò Tí ó Ṣeyebíye”?

● Sólómọ́nì Ọba kọ̀wé pé: “Wúrà wà, àti ọ̀pọ̀ yanturu iyùn pẹ̀lú; ṣùgbọ́n ètè ìmọ̀ jẹ́ ohun èlò tí ó ṣeyebíye.” (Òwe 20:15) Ọjọ́ pẹ́ táwọn èèyàn ti ka wúrà sí nǹkan iyebíye, bákan náà nígbà ayé Sólómọ́nì àwọn èèyàn mọyì iyùn gan-an ni. Àmọ́, ètè wa tún lè ṣeyebíye ju àwọn nǹkan yìí lọ. Lọ́nà wo? Kì í ṣe bí ètè wa ṣe fani mọ́ra tó ló máa jẹ́ kó ṣeyebíye, ṣùgbọ́n ohun tó ń ti ẹnu wa jáde ló máa fi hàn bẹ́ẹ̀.

Àwọn nǹkan tí ètè tó ṣeyebíye máa ń mú jáde ni, ohun rere, inú rere àti ìfẹ́. Bákan náà, “ètè ìmọ̀” máa ń sọ òótọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó wà nínú Bíbélì. Ìwé àtọdúnmọ́dún yìí kún fún ọgbọ́n àti òtítọ́ nípa Ẹlẹ́dàá wa àti ìmọ̀ràn tí kò láfiwé nípa bá a ṣe máa gbé ìgbésí ayé wa.—Jòhánù 17:17.

Ó bani nínú jẹ́ pé ọ̀pọ̀ èèyàn máa ń lo ètè wọn lọ́nà tí kò dáa nípa sísọ àwọn nǹkan tí kì í ṣe òótọ́ nípa Ọlọ́run. Bí àpẹẹrẹ, àwọn kan máa ń dá Ọlọ́run lẹ́bi nítorí ìwà ìrẹ́jẹ àti ìjìyà tó ń ṣẹlẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ sì rèé, àfọwọ́fà ọmọ aráyé ni èyí tó pọ̀ jù nínú wọn. Lórí èyí, Òwe 19:3 sọ pé: “Àwọn kan ń ba ayé ara wọn jẹ́ nípasẹ̀ ìwà òmùgọ̀ wọn, lẹ́yìn náà, wọ́n wá ń dá Olúwa lẹ́bi.”—Today’s English Version.

Àwọn kan máa ń sọ ètè wọn di ohun tí kò ṣeyebíye nípa sísọ ọ̀rọ̀ tí kì í ṣòótọ́, ṣíṣe òfófó apanilára àti sísọ̀rọ̀ àwọn míì láìdáa. Lórí èyí, Òwe 26:23 lo àfiwé tó lágbára kan, ó sọ pé: “Bí fàdákà fẹ́ẹ́rẹ́ tí a fi bo àpáàdì ni ètè tí ń jó belebele pa pọ̀ pẹ̀lú ọkàn-àyà búburú.” Bíi “fàdákà fẹ́ẹ́rẹ́” tí ó bo àpáàdì, “ètè tí ń jó belebele” lè máa sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ìmọ̀lára tó lágbára, kó sì dà bíi pé òótọ́ ló ń sọ, nígbà tó jẹ́ pé látinú “ọkàn-àyà búburú” ló ti ń sọ̀rọ̀.—Òwe 26:24-26.

Ó dájú pé, irú ìwà búburú bẹ́ẹ̀ kò pa mọ́ lọ́jú Ọlọ́run. Ó mọ irú èèyàn tá a jẹ́ gan-an! Ìdí nìyẹn tí Jésù Kristi fi sọ pé: “Kọ́kọ́ fọ inú ife àti àwopọ̀kọ́ mọ́, kí òde rẹ̀ pẹ̀lú le di èyí tí ó mọ́.” (Mátíù 23:26) Òótọ́ pọ́ńbélé lọ̀rọ̀ yìí o! Bákan náà, bí inú wa bá mọ́, tí òtítọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sì wà nínú ọkàn wa, ó máa hàn nínú ọ̀rọ̀ wa. Kí nìyẹn máa wá yọrí sí? Ètè wa á di “ohun èlò tí ó ṣeyebíye,” ní pàtàkì jù lọ lójú Ọlọ́run.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 19]

Ètè àwọn ọlọ́gbọ́n jẹ́ “ohun èlò tí ó ṣeyebíye”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́