ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 81 ojú ìwé 190-ojú ìwé 191 ìpínrọ̀ 2
  • Ìwàásù Orí Òkè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwàásù Orí Òkè
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó Mú Kí Jésù Jẹ́ Olùkọ́ Ńlá
    Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Olùkọ́ Ńlá Náà
  • Ẹ Máa Ṣe Rere
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • “Mo Pè Yín Ní Ọ̀rẹ́”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ó Yẹ Kí O Kẹ́kọ̀ọ́ Nípa Ọlọ́run
    Ìwọ Lè Di Ọ̀rẹ́ Ọlọ́run!
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 81 ojú ìwé 190-ojú ìwé 191 ìpínrọ̀ 2
Jésù ń wàásù fún ọ̀pọ̀ èèyan lórí òkè

Ẹ̀KỌ́ 81

Ìwàásù Orí Òkè

Lẹ́yìn tí Jésù yan àwọn àpọ́sítélì méjìlá náà, ó sọ̀ kalẹ̀ látorí òkè, ó sì lọ síbi táwọn èrò rẹpẹtẹ jókòó sí. Àwọn èèyàn náà wá láti Gálílì, Jùdíà, Tírè, Sídónì, Síríà àtàwọn ìlú míì tó wà ní ìsọdá Odò Jọ́dánì. Wọ́n gbé àwọn tó ní oríṣiríṣi àìsàn wá sọ́dọ̀ Jésù àtàwọn tí ẹ̀mí èṣù ń yọ lẹ́nu, ó sì wo gbogbo wọn sàn. Lẹ́yìn ìyẹn, Jésù jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ òkè náà, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀. Ó sọ àwọn nǹkan tá a gbọ́dọ̀ máa ṣe tá a bá fẹ́ di ọ̀rẹ́ Ọlọ́run. A gbọ́dọ̀ jẹ́ kí Jèhófà máa tọ́ wa sọ́nà, ká sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀. Àmọ́, a ò lè nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run tá ò bá nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn. A gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ gbogbo èèyàn, ká sì máa ṣe dáadáa sí wọn títí kan àwọn tó kórìíra wa pàápàá.

Jésù sọ pé: ‘Kì í ṣe àwọn ọ̀rẹ́ rẹ nìkan ló yẹ kó o nífẹ̀ẹ́, ó yẹ kó o nífẹ̀ẹ́ àwọn ọ̀tá ẹ náà, kó o sì máa dárí jì wọ́n. Tẹ́nì kan bá sọ pé o ṣẹ òun, tètè lọ bá a, kó o sì bẹ̀ ẹ́ pé kó má bínú. Ohun tó o bá sì fẹ́ káwọn èèyàn ṣe sí ẹ ni kíwọ náà máa ṣe sí wọn.’

Jésù ń wàásù fún ọ̀pọ̀ èèyan lórí òkè

Jésù tún sọ pé ká má ṣe jẹ́ kí ọ̀rọ̀ owó ká wa lára jù. Ó sọ pé: ‘Ó dáa kéèyàn jẹ́ ọ̀rẹ́ Jèhófà ju kéèyàn jẹ́ olówó lọ. Torí pé àwọn olè lè jí owó èèyàn lọ, àmọ́ kò sẹ́ni tó lè jí àwọn ìbùkún tá à ń rí látinú àjọṣe wa pẹ̀lú Jèhófà. Ẹ má dààmú jù nípa ohun tẹ́ ẹ máa jẹ, ohun tẹ́ ẹ máa mu tàbí ohun tẹ́ ẹ máa wọ̀. Ẹ wo àwọn ẹyẹ, wọn ò ṣiṣẹ́, àmọ́ Jèhófà máa ń rí i pé wọ́n ní oúnjẹ tó pọ̀ láti jẹ. Tẹ́ ẹ bá ń da ara yín láàmú jù, ìyẹn ò ní fi ọjọ́ kan kún ọjọ́ ayé yín. Ẹ rántí pé Jèhófà mọ gbogbo ohun tẹ́ ẹ nílò.’

Àwọn èèyàn yẹn ò rẹ́ni tó sọ̀rọ̀ bíi Jésù rí. Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn wọn ò kọ́ wọn láwọn ohun tí Jésù kọ́ wọn. Àmọ́, kí ló mú kí Jésù mọ èèyàn kọ́ dáadáa? Ìdí ni pé ohun tí Jèhófà sọ ló ń kọ́ àwọn èèyàn.

“Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ mi, torí oníwà tútù àti ẹni tó rẹlẹ̀ ní ọkàn ni mí, ara sì máa tù yín.”​—Mátíù 11:29

Ìbéèrè: Kí la gbọ́dọ̀ ṣe tá a bá fẹ́ di ọ̀rẹ́ Jèhófà? Báwo ni Jèhófà ṣe fẹ́ ká máa ṣe sáwọn èèyàn?

Mátíù 4:24–5:48; 6:19-34; 7:28, 29; Lúùkù 6:17-31

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́