ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w94 2/15 ojú ìwé 30
  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
w94 2/15 ojú ìwé 30

Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994

MARCH

1. Awọn eniyan tí ń rìn ní òkùnkùn rí ìmọ́lẹ̀ ńlá: awọn tí ń gbé ilẹ̀ òjìji ikú, lara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.​—⁠Isa. 9:⁠2. w-YR 4/1/93 11, 12

2. Maa sá fun ifẹkufẹẹ èwe: sì maa lépa òdodo, igbagbọ, ifẹ, alaafia, pẹlu awọn ti ń ké pe Oluwa lati inu ọkàn funfun wá.​—⁠2 Tim. 2:⁠22. w-YR 4/15/93 6, 10, 11

3. Ọ̀rọ̀ wọnyi, ti mo palaṣẹ fun ọ ni oni, ki o maa wà ni àyà rẹ.​—⁠Deut. 6:⁠6. w-YR 11/1/92 7, 8

4. Wèrè eniyan yi ọ̀nà rẹ̀ po: nigba naa ni àyà rẹ̀ binu si Oluwa.​—⁠Owe 19:⁠3. w-YR 11/15/92 9, 10a

5. Kò sí ọ̀kankan tí ó dàbí rẹ laaarin awọn ọlọrun, óò Jehofa, bẹẹ ni kò sí awọn iṣẹ eyikeyii tí ó dàbí tìrẹ.​—⁠Orin Da. 86:⁠8, NW. w-YR 12/15/92 14, 15

6. Emi ni ìmọ́lẹ̀ ayé; ẹni tí ó bá tọ̀ mi lẹ́yìn ki yoo rìn ninu òkùnkùn, ṣugbọn yoo ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.​—⁠Joh. 8:⁠12. w-YR 1/15/93 8, 10, 11

7. Oluwa ni onidaajọ wa, Oluwa ni olofin wa, Oluwa ni ọba wa; oun o gbà wa là.​—⁠Isa. 33:⁠22. w-YR 2/1/93 6, 8

8. Simoni, iwọ ti rò ó sí? lọwọ ta ni awọn ọba ayé ti maa ń gba owóòde? lọwọ awọn ọmọ wọn, tabi lọwọ awọn alejo?​—⁠Matt. 17:⁠25. w-YR 10/15/92 15, 16a

9. Ẹ ma si ṣe mu ẹmi mimọ Ọlọrun binu, [eyi ti] a fi ṣe edidi yin de ọjọ idande.​—⁠Efe. 4:⁠30. w-YR 9/15/92 15, 17, 18a

10. Ta ni ó dàbí Jehofa Ọlọrun wa, ẹni tí ó fi ibi gíga lókèlókè ṣe ibugbe rẹ̀? Ó ń rẹ araarẹ̀ sílẹ̀ lati wo ọ̀run ati ilẹ̀-ayé.​—⁠Orin Da. 113:​5, 6, NW. w-YR 11/15/92 8, 9

11. Ẹ̀yin gbọ́dọ̀ pè é padà sí ọkàn-àyà yín [àlàyé etí-ìwé, “gbọ́dọ̀ pè padà sí èrò-inú yìn”] pé Jehofa ni Ọlọrun tòótọ́.​—⁠Deut. 4:39, NW. w-YR 3/1/93 1-⁠3

12. Emi ni [Jehofa, NW]: eyi ni orukọ mi: ògo mi ni emi kì yoo fi fún ẹlòmíràn, bẹẹni emi kì yoo fi iyin mi fún ère gbígbẹ́.​—⁠Isa. 42:⁠8. w-YR 1/15/93 7, 8, 10a

13. Gbogbo awọn orílẹ̀-èdè tí iwọ ti ṣe yoo fúnraawọn wá, wọn yoo sì tẹríba niwaju rẹ, óò Jehofa, wọn yoo sì fi ògo fún orukọ rẹ.​—⁠Orin Da. 86:⁠9, NW. w-YR 12/15/92 17

14. Oluwa, iwọ ni ó yẹ lati gba ògo ati ọlá ati agbara: Nitori pe iwọ ni o dá ohun gbogbo, ati nitori ifẹ-inu rẹ ni wọn fi wà ti a sì dá wọn.​—⁠Ìfi. 4:⁠11. w-YR 2/1/93 9-⁠11

15. Emi gbìn, Apollo bomirin; ṣugbọn Ọlọrun ni ń mú ibisi wá. Ǹjẹ́ kì í ṣe ẹni tí ó ń gbìn nǹkankan, bẹẹ ni kì í ṣe ẹni ti ń bomirin; bikoṣe Ọlọrun tí ó ń mú ibisi wá.​—⁠1 Kor. 3:​6, 7. w-YR 9/1/92 11, 12a

16. Adura igbagbọ yoo si gba alaisan naa là, Oluwa yoo si gbe e dide; bí ó bá sì ṣe pe o ti dẹṣẹ, a o dáríjì í.​—⁠Jak. 5:⁠15. w-YR 9/15/92 17, 18

17. Kí aya ní ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ fún ọkọ rẹ̀.​—⁠Efe. 5:⁠33, NW. w-YR 10/15/92 12, 13

18. Ọlọrun, ṣaanu fun mi, gẹgẹ bi iṣeun ifẹ rẹ̀: gẹgẹ bi irọnu ọpọ aanu rẹ, nu irekọja mi nù kuro.​—⁠Orin Da. 51:⁠1. w-YR 3/15/93 10, 11

19. Nitori naa ẹ lọ, ki ẹ maa sọ gbogbo eniyan orilẹ-ede di ọmọ-ẹ̀yìn.​—⁠Matt. 28:⁠19. w-YR 1/15/93 11, 12

20. Yoo si ṣe ni ọjọ ìkẹyìn, a o fi oke ile Oluwa kalẹ lori awọn oke nla, . . . gbogbo orilẹ-ede ni yoo si wọ́ si inu rẹ̀.​—⁠Isa. 2:⁠2. w-YR 4/1/93 5, 6

21. Ìmọ̀ a maa fẹ̀, ṣugbọn ifẹ ni gbéniró.​—⁠1 Kor. 8:⁠1. w-YR 11/15/92 16, 17b

22. Dẹtí rẹ silẹ, óò Jehofa. Dá mi lóhùn, nitori tí mo jẹ́ ẹni ti a pọ́nlójú ati òtòṣì. Óò dákun daabobo ọkàn mi, nitori ti mo jẹ́ aduroṣinṣin. Gba iranṣẹ rẹ​—⁠ti ń ní igbẹkẹle ninu rẹ là​—⁠iwọ ni Ọlọrun mi.​—⁠Orin Da. 86:​1, 2, NW. w-YR 12/15/92 3, 4

23. Ẹyin ọmọ mi, ẹ pa araayin mọ́ kuro ninu oriṣa.​—⁠1 Joh. 5:⁠21. w-YR 1/15/93 19, 21-⁠23a

24. Iwọ sọ̀rọ̀ bi ọ̀kan ninu awọn obinrin alaimoye ti i sọ̀rọ̀; kinla! awa o ha gba ire lọwọ Ọlọrun, ki a má si gba ibi!​—⁠Jobu 2:⁠10. w-YR 2/1/93 19

25. Kí ẹ di titun ninu ipá tí ń mú èrò-inú yín ṣiṣẹ́.​—⁠Efe. 4:⁠23, NW. w-YR 3/1/93 11, 12a

26. Iwọ tobi o sì ń ṣe awọn ohun àgbàyànu; iwọ ni Ọlọrun, iwọ nìkan.​—⁠Orin Da. 86:⁠10, NW. w-YR 12/15/92 18-⁠20

27. Ṣugbọn nigba ti ó rí ọpọ eniyan, àánú wọn ṣe é, nitori ti àárẹ̀ mú wọn, wọ́n sì túka kiri bi awọn agutan ti kò ni oluṣọ.​—⁠Matt. 9:⁠36. w-YR 4/1/93 8a

28. Ifẹ kii yẹ̀ lae.​—⁠1 Kor. 13:⁠8. w-YR 2/15/93 15, 16

29. [Ki sì ni, NW] ohun tí Oluwa beere lọwọ rẹ, bikoṣe ki o ṣe otitọ, ki o sì fẹ àànú, ati ki o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹlu Ọlọrun rẹ?​—⁠Mika 6:⁠8. w-YR 4/15/93 18, 19

30. Ta ni o lè mọ iṣina rẹ̀? Wẹ̀ mi mọ́ kuro ninu ìṣìṣe ikọkọ mi. Fa iranṣẹ rẹ sẹ́yìn pẹlu kuro ninu ẹ̀ṣẹ̀ ìkùgbù: maṣe jẹ ki wọn ki o jọba lori mi: nigba naa ni emi o duro ṣinṣin, emi o si ṣe alaijẹbi kuro ninu ẹ̀ṣẹ̀ nla nì. Jẹ ki ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ati ìṣàrò ọkan mi, ki o ṣe itẹwọgba ni oju rẹ, Oluwa, agbara mi, ati oludande mi.​—⁠Orin Da. 19:​12-⁠14. w-YR 11/15/92 5a

31. Ẹyin ọmọ, ẹ maa gbọ ti awọn obi yin ninu Oluwa: nitori pe eyi ni o tọ́. Bọwọ fun baba ati iya rẹ eyi ti iṣe ofin ikinni pẹlu ileri, Ki o lè dara fun ọ, ati ki iwọ ki o lè wà pẹ ni ayé.​—⁠Efe. 6:​1-⁠3. w-YR 10/15/92 17, 18

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́