ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w94 2/15 ojú ìwé 31
  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
w94 2/15 ojú ìwé 31

Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún 1994

APRIL

1. Ẹ máa gbọ́ ti awọn ti ń ṣe olori yin, ki ẹ si maa tẹriba fun wọn: nitori wọn ń ṣọ ẹṣọ nitori ọkàn yin, bi awọn ti yoo ṣe iṣiro.​—⁠Heb. 13:⁠17. w-YR 9/1/92 8

2. Ijọba rẹ̀ yoo sì jẹ́ lati òkun dé òkun, ati lati odò titi de opin ayé.​—⁠Sek. 9:⁠10. w-YR 9/15/92 8, 9b

3. Kristi [Messia], Ọmọ Ọlọrun alaaye ni iwọ ń ṣe.​—⁠Matt. 16:⁠16. w-YR 10/1/92 1, 2

4. Oluwa ni i fi ọgbọ́n funni: lati ẹnu rẹ̀ jade ni ìmọ̀ ati oye ti i wá.​—⁠Owe 2:⁠6. w-YR 11/1/92 10, 11

5. Ẹ mu gbogbo idamẹwaa wá si ile iṣura, ki ounjẹ baa le wà ni ile mi, ẹ si fi eyi dan mi wò nisinsinyi, bi emi ki yoo ba . . . sí tú ibukun jade fun yin, tobẹẹ ti ki yoo si àyè tó lati gbà á.​—⁠Mal. 3:⁠10. w-YR 12/1/92 10, 15, 16a

6. Nigba ti Israeli jade kuro ni Egipti, ti ara-ile Jakobu kuro ninu ajeji ede eniyan; Juda ni ibi mimọ rẹ̀, Israeli ni ijọba rẹ̀.​—⁠Orin Da. 114:​1, 2. w-YR 11/15/92 12, 13

7. Ẹ̀yin baba, ẹ máṣe máa sún awọn ọmọ yín bínú, ṣugbọn ẹ máa báa lọ ní títọ́ wọn dàgbà ninu ìbáwí ati ìlànà èrò-orí Jehofa.​—⁠Efe. 6:⁠4, NW. w-YR 10/15/92 9, 10a

8. Dafidi sì tẹ́síwájú lati fi aworan ìkọ́lé naa fún Solomoni ọmọkùnrin rẹ̀ . . . èyí tí oun ti ní nípasẹ̀ ìmísí.​—⁠1 Kron. 28:​11, 12, NW. w-YR 1/1/93 17, 18

9. Dide, tàn ìmọ́lẹ́: nitori ìmọ́lẹ̀ rẹ dé, ogo Oluwa si yọ lara rẹ. Nitori kiyesi i, . . . Oluwa yoo yọ lara rẹ, a ó sì rí ogo rẹ̀ lara rẹ.​—⁠Isa. 60:​1, 2. w-YR 1/15/93 15, 16

10. Ọlọrun, gbà mi lọwọ ẹbi ẹ̀jẹ̀, iwọ Ọlọrun igbala mi: ahọ́n mi yoo sì maa kọrin òdodo rẹ kíkan.​—⁠Orin Da. 51:⁠14. w-YR 3/15/93 12a

11. Ará, bi a tilẹ mú eniyan ninu ìṣubú kan, kí ẹyin tí iṣe ti ẹmi kí ó mú iru ẹni bẹẹ bọ̀ sípò ní ẹmi ìwà tútù; kí iwọ tikaraarẹ maa kiyesara, kí a má ba dan iwọ naa wò pẹlu.​—⁠Gal. 6:⁠1. w-YR 2/1/93 9, 10a

12. Ṣaanu fun mi, Oluwa: nitori iwọ ni emi ń képè lojoojumọ. Mu ọkàn iranṣẹ rẹ yọ̀: Oluwa, nitori iwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.​—⁠Orin Da. 86:​3, 4. w-YR 12/15/92 6, 7

13. A fi ofin de obinrin niwọn ìgbà ti ọkọ rẹ̀ bá wà laaye; ṣugbọn bi ọkọ rẹ̀ ba kú, o di ominira lati ba ẹnikẹni tÍ ó wù ú gbeyawo; kiki ninu Oluwa.​—⁠1 Kor. 7:⁠39. w-YR 2/15/93 3, 4a

14. Kí ẹ bọ́ àkópọ̀-ànímọ́-ìwá ogbologboo sílẹ̀ èyí tí ó bá ìlà ipa-ọ̀nà ìwà yín ti àtijọ́ ṣe déédéé tí a sì ń sọ di ìbàjẹ́ ní ìbámu pẹlu awọn ìfẹ́-ọkàn rẹ̀ atannijẹ.​—⁠Efe. 4:⁠22, NW. w-YR 3/1/93 8, 9a

15. Ẹ wá, ẹ jẹ ki a yipada si Oluwa: . . . awa o . . . tẹramọ ati mọ Oluwa.​—⁠Hos. 6:​1-⁠3. w-YR 4/15/93 13, 14

16. Awọn eniyan ti ń rin ni òkùnkùn ri ìmọ́lẹ̀ nla: awọn ti ń gbe ilẹ̀ ojiji ikú, lara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.​—⁠Isa. 9:⁠2. w-YR 4/1/93 12-⁠14

17. Ọsan kan ati oru kan ni mo wà ninu ibú. Ni irin-ajo nigbakuugba, ninu ewu omi, . . . ninu ewu ni aginju, ninu ewu loju òkun.​—⁠2 Kor. 11:​25, 26. w-YR 9/1/92 9

18. Nitori orukọ rẹ, Oluwa, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, nitori tí ó tobi.​—⁠Orin Da. 25:⁠11. w-YR 9/15/92 11, 12

19. Kí ni yoo sì jẹ́ àmì wíwàníhìn-ín rẹ ati ti ìparí ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan?​—⁠Matt. 24:⁠3, NW. w-YR 10/1/92 9, 10a

20. Emi ó pa ọgbọ́n awọn ọlọ́gbọ́n run, emi ó si sọ òye awọn olóye di asan.​—⁠1 Kor. 1:⁠19. w-YR 11/1/92 13-⁠15a

21. Ẹ̀yin baba, ẹ máṣe máa sún awọn ọmọ yín bínú, ṣugbọn ẹ máa báa lọ ní títọ́ wọn dàgbà ninu ìbáwí ati ìlànà èrò-orí ti Jehofa.​—⁠Efe. 6:⁠4, NW. w-YR 10/15/92 9, 13, 14a

22. Oun kìí ṣe si wa gẹgẹ bi ẹ̀ṣẹ̀ wa; bẹẹ ni kìí san án fun wa gẹgẹ bi aiṣedeedee wa.​—⁠Orin Da. 103:⁠10. w-YR 11/15/92 6a

23. Ẹ mu gbogbo idamẹwaa wá si ile iṣura, . . . ẹ sì fi eyi dán mi wò nisinsinyi, bi emi ki yoo ba . . . tú ibukun jade fun yin, tobẹẹ ti ki yoo si àyè tó lati gbà á.​—⁠Mal. 3:⁠10. w-YR 12/1/92 10-⁠12a

24. Ẹyin ó gba agbara, nigba ti ẹmi mimọ bá bà le yin: ẹ o sì maa ṣe ẹlẹ́rìí mi . . . titi de opin ilẹ̀-ayé.​—⁠Iṣe 1:⁠8. w-YR 1/1/93 6, 7a

25. [Jehofa, NW] Ọlọrun rẹ ajonirun iná ni, Ọlọrun owú.​—⁠Deut. 4:⁠24. w-YR 1/15/93 5, 13b

26. Nitori naa gbogbo ohunkohun ti ẹyin ba ń fẹ ki eniyan ki o ṣe si yin, bẹẹ ni ki ẹyin ki o sì ṣe sí wọn gẹgẹ; nitori eyi ni ofin ati awọn wolii.​—⁠Matt. 7:⁠12. w-YR 2/1/93 4, 5a

27. O sàn lati jokoo ni igun oke àjà, ju pẹlu onija obinrin lọ ninu ile ajumọgbe.​—⁠Owe 21:⁠9. w-YR 2/15/93 1, 2a

28. Nitori naa, èyí ni mo ń wí tí mo sì ń jẹ́rìí sí ninu Oluwa, pé kí ẹ máṣe máa bá a lọ mọ́ ní rírìn gan-an gẹ́gẹ́ bí awọn orílẹ̀-èdè pẹlu ti ń rìn ninu àìlérè èrò-inú wọn.​—⁠Efe. 4:⁠17, NW. w-YR 3/1/93 7, 8

29. Emi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fun ọ, ati ẹ̀ṣẹ̀ mi ni emi kò si fi pamọ. Emi wi pe, emi o jẹ́wọ́ irekọja mi fun Oluwa: iwọ sì dari ẹbi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.​—⁠Orin Da. 32:⁠5. w-YR 3/15/93 1, 8

30. Oluwa yoo yọ lara rẹ, a o sì rí ogo rẹ̀ lara rẹ. Awọn Keferi yoo wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ.​—⁠Isa. 60:​2, 3. w-YR 4/1/93 9, 10

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́