ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w04 5/1 ojú ìwé 32
  • Ǹjẹ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ń Fún ọ Lókun?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ń Fún ọ Lókun?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
w04 5/1 ojú ìwé 32

Ǹjẹ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ń Fún ọ Lókun?

KÍ LO máa ń ṣe nígbà tó o bá dojú kọ ìṣòro? Nígbà tí Sátánì dán Jésù wò, rírántí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó bá ipò tó wà mu ló ràn án lọ́wọ́. (Mátíù 4:1-11) Bákan náà, nígbà tí àwọn ìṣòro kan ń bá Dáfídì Ọba fínra, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ló fún un lókun. Ó sọ pé: “Nígbà tí ìrònú tí ń gbé mi lọ́kàn sókè di púpọ̀ nínú mi, ìtùnú tìrẹ ni ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣìkẹ́ ọkàn mi.”—Sáàmù 94:19.

Lọ́nà kan náà, rírántí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a yàn láàyò lè tù wá nínú tàbí kó fún wa lókun nígbà tá a bá wà nínú ìṣòro. Bí àpẹẹrẹ, arákùnrin Rex, tó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kàndínláàádọ́rùn-ún báyìí, ti wà nínú iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún láti ọdún 1931. Síbẹ̀, ó sọ pé: “Mo sábà máa ń wò ó pé mi ò tóótun nígbà tí wọ́n bá ní kí n bójú tó iṣẹ́ àkànṣe kan nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́.” Báwo ló ṣe borí ìṣòro yìí? “Mo máa ń rántí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí mo yàn láàyò, ìyẹn Òwe 3:5, èyí tó sọ pé: ‘Fi gbogbo ọkàn-àyà rẹ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, má sì gbára lé òye tìrẹ.’ Rírántí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí àti fífi í sílò ló ràn mí lọ́wọ́ láti ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ mi láṣeyọrí.”

Kódà, àwọn ògo wẹẹrẹ pàápàá ń jàǹfààní látinú níní ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tí wọ́n yàn láàyò. Ọmọ ọlọ́dún mẹ́fà kan tó ń jẹ́ Jack sọ pé ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí òun yàn láàyò ni Mátíù 24:14. Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí máa ń sún un láti tẹ̀ lé àwọn òbí rẹ̀ lọ wàásù. Ó sọ pé: “Mo fẹ́ràn kí n máa tẹ̀ lé màmá mi, bàbá mi, àti ẹ̀gbọ́n mi obìnrin lọ wàásù ní gbogbo ọjọ́ Sátidé.”

Bíi ti Jésù, ṣé ìwọ náà máa ń rí àwọn ohun kan tó lè dán ìgbàgbọ́ rẹ wò lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan? Nígbà náà, o lè fi Fílípì 4:13 ṣe ọ̀kan lára àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó o yàn láàyò. Bíi ti Dáfídì Ọba, ǹjẹ́ ‘ìrònú tí ń gbéni lọ́kàn sókè’ máa ń dààmú rẹ? Bó bá rí bẹ́ẹ̀, rírántí Fílípì 4:6, 7 lè ṣèrànwọ́ fún ọ láti fara dà á. Ǹjẹ́ o máa ń ṣàníyàn nígbà mìíràn pé iṣẹ́ ìsìn rẹ sí Ọlọ́run kò já mọ́ nǹkan kan? Nígbà náà, fífi 1 Kọ́ríńtì 15:58 sọ́kàn yóò fún ọ lókun.

Bá a bá ń rántí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wúlò gan-an fún wa, ó fi hàn pé à ń jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa sa agbára nígbèésí ayé wa. (Hébérù 4:12) Irú àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a yàn láàyò bẹ́ẹ̀ lè fún wa lókun, wọ́n sì tún lè tù wá nínú. —Róòmù 15:4.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́