ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w06 2/1 ojú ìwé 32
  • Ǹjẹ́ o Dà Bí Igi Ṣẹkẹṣẹkẹ?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ o Dà Bí Igi Ṣẹkẹṣẹkẹ?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
w06 2/1 ojú ìwé 32

Ǹjẹ́ o Dà Bí Igi Ṣẹkẹṣẹkẹ?

NÍ ABÚLÉ kan tó wà nítòsí ìlú Port Moresby, lórílẹ̀-èdè Papua New Guinea, àwọn oníwàásù méjì kan ń padà bọ̀ wá sílé látẹnu iṣẹ́ ìwàásù wọn. Bí wọ́n ti ń bọ̀ lọ́nà, wọ́n rí igi kan tó lẹ́wà gan-an. Èyí tó dàgbà jù láàárín àwọn ọkùnrin náà sọ pé: “Áà, igi ṣẹkẹṣẹkẹ ni!” Ó wá yíjú sí ẹnì kejì rẹ̀ ó sì ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ, ó ní: “Igi tó ń rú lọ́dọọdún ni. Kò dà bí ọ̀pọ̀ igi mìíràn nílẹ̀ olóoru, ọdọọdún ló máa ń wọ́wé tí yóò sì dà bíi pé ó ti kú. Àmọ́, nígbà tójò bá rọ̀, á sọjí, á sì yọ òdòdó, yóò sì tún fi ẹwà rẹ̀ hàn padà.”

A lè rí ẹ̀kọ́ kan kọ́ lára igi ṣẹkẹṣẹkẹ. Gẹ́gẹ́ bí ohun táwọn onímọ̀ nípa igi sọ, igi yìí wà lára àwọn igi olódòdó márùn-ún tó lẹ́wà jù lọ láyé. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ewé àti òdòdó rẹ̀ máa ń rẹ̀ dà nù nígbà ẹ̀rùn, igi yìí máa ń tọ́jú omi pa mọ́ sára. Gbòǹgbò igi náà lágbára gan-an, ó sì lè ta yí àwọn àpáta tó wà lábẹ́ ilẹ̀ ká. Nítorí bẹ́ẹ̀, mìmì kan ò lè mì í nígbà tí afẹ́fẹ́ líle bá ń fẹ́. Ní ṣókí, igi yìí rọ́kú nítorí pé kò sí inú ipò tí ò ti lè dàgbà.

A lè bá ara wa nínú ipò tó máa dán bí ìgbàgbọ́ wa ti lágbára tó wò. Kí ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti fara da ipò náà? Bíi ti igi ṣẹkẹṣẹkẹ, a óò máa mu omi Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó ń fúnni ní ìyè, a ó sì máa tọ́jú omi náà pa mọ́ sọ́kàn wa. A tún gbọ́dọ̀ fìdí múlẹ̀ dáadáa nínú ‘àpáta wa,’ ìyẹn Jèhófà àti ètò rẹ̀. (2 Sámúẹ́lì 22:3) Ká sòótọ́, igi ṣẹkẹṣẹkẹ jẹ́ igi kan tó ń ránni létí pé nínú ipò tó le koko pàápàá, a lè jẹ́ alágbára nípa tẹ̀mí ká sì máa ṣe ohun tó bá Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mu tá a bá ń lo àwọn ohun tí Jèhófà ń pèsè fún wa. Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, a óò “jogún àwọn ìlérí” tó ṣe fún wa, títí kan ìlérí iyè àìnípẹ̀kun.—Hébérù 6:12; Ìṣípayá 21:4.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́