ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w11 5/1 ojú ìwé 7
  • Àsọtẹ́lẹ̀ 4. Kò Sí Ìfẹ́ Nínú Ìdílé Mọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 4. Kò Sí Ìfẹ́ Nínú Ìdílé Mọ́
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìrànlọ́wọ́ fún Àwọn tí Wọ́n Ń Fìyà Jẹ Nínú Ilé
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Kí Ló Dé Táwọn Ọkùnrin Kan Fi Máa Ń Lu Ìyàwó Wọn?
    Jí!—2001
  • Ìwọ́ Lè Borí Àwọn Ìṣòro Tí Ń Ṣe Ìdílé Lọ́ṣẹ́
    Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé
  • Fífìyà Jẹ Àwọn Obìnrin Ti Di Ìṣòro Tó Kárí Ayé
    Jí!—2008
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
w11 5/1 ojú ìwé 7

Àsọtẹ́lẹ̀ 4. Kò Sí Ìfẹ́ Nínú Ìdílé Mọ́

‘Àwọn èèyàn kì yóò ní ìfẹ́ tó yẹ fún àwọn ìdílé wọn.’—2 TÍMÓTÌ 3:1-3, God’s Word Bible

● Obìnrin kan tó ń jẹ́ Chris jẹ́ òṣìṣẹ́ àwùjọ tó ń ṣèrànwọ́ fún àwọn tí wọ́n hùwà ipá sí nínú ilé ní North Wales. Ọ̀gbẹ́ni Chris sọ pé, “Mo rántí ọmọbìnrin kan tó wọlé wá, wọ́n ti lù ú nílùkulù débi pé, mi ò dá a mọ̀ mọ́. Ẹ̀dùn ọkàn àwọn obìnrin míì pọ̀ débi pé, wọn kò ní lè gbójú sókè wo ìwọ tó ò ń bá wọn sọ̀rọ̀.”

KÍ NI Ẹ̀RÍ FI HÀN? Ní orílẹ̀-èdè kan nílẹ̀ Áfíríkà, nǹkan bí obìnrin kan nínú mẹ́ta ni wọ́n ti bá ṣèṣekúṣe láti kékeré. Nínú ìwádìí kan tí wọ́n ṣe ní orílẹ̀-èdè yìí kan náà, ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ ìdajì àwọn ọkùnrin tí wọ́n fọ̀rọ̀ wá lẹ́nu wò ló gbà pé kò burú láti lu ìyàwó wọn. Àmọ́, kì í ṣe àwọn obìnrin nìkan ni wọ́n ń hùwà ipá sí nínú ilé. Bí àpẹẹrẹ, ní orílẹ̀-èdè Kánádà nǹkan bí ọkùnrin mẹ́ta nínú mẹ́wàá ni ìyàwó wọ́n ti lù nílùkulù tàbí hùwà ìkà sí.

ÀTAKÒ TÁWỌN ÈÈYÀN Ń ṢE Ó ti pẹ́ tí ìwà ipá ti ń ṣẹlẹ̀ nínú ilé. Àmọ́ ìyàtọ̀ tó wà níbẹ̀ lóde òní ni pé, wọ́n ń jẹ́ káwọn èèyàn gbọ́ nípa rẹ̀ ju ti tẹ́lẹ̀ lọ.

ṢÉ ÀTAKÒ YÌÍ LẸ́SẸ̀ NÍLẸ̀? Wọ́n ń jẹ́ káwọn èèyàn gbọ́ gan-an nípa ìwà ipá inú ilé láti ohun tó lé lógún ọdún sí àkókò yìí. Àmọ́, ṣé bí wọ́n ṣe ń kéde ìṣòro yìí fáyé gbọ́ ti jẹ́ kí ìwà ipá inú ilé dín kù? Rárá o. Ńṣe ni àìsí ìfẹ́ nínú ìdílé túbọ̀ ń pọ̀ sí i.

KÍ NI ÈRÒ RẸ? Ṣé ohun tó wà nínú ìwé 2 Tímótì 3:1-3 ló ń ṣẹ? Ṣé òótọ́ ni pé ọ̀pọ̀ èèyàn kò ní ìfẹ́ tó yẹ fún àwọn ìdílé wọn?

Àsọtẹ́lẹ̀ karùn-ún tó ń ṣẹ lákòókò yìí kan ayé tó jẹ́ ilé wa. Ẹ jẹ́ ká ṣàyẹ̀wò ohun tí Bíbélì sọ nípa rẹ̀.

[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 7]

“Wọ́n sọ pé, ìwà ipá inú ilé jẹ́ ìwà ọ̀daràn tí wọn kì í sọ síta láwùjọ wa lónìí. Ìwádìí fi hàn pé ó máa ń tó ìgbà márùndínlógójì [35] ni ọkọ kan máa ń hùwà ìkà sí ìyàwó rẹ̀ kí obìnrin náà tó sọ fún ọlọ́pàá.”​—AGBỌ̀RỌ̀SỌ ÀWÙJỌ TÓ Ń ṢÈRÀNWỌ́ FÚN ÀWỌN TÍ WỌ́N HÙWÀ IPÁ SÍ NÍNÚ ILÉ NÍLẸ̀ WALES.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́