ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w13 5/1 ojú ìwé 15
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ọlọ́run Máa Dárí Jì Mí?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ọlọ́run Tó “Ṣe Tán Láti Dárí Jini”
    Sún Mọ́ Jèhófà
  • Tí Ọlọ́run Bá Ti Dárí Ẹ̀ṣẹ̀ Jini, Ṣé Ó Máa Ń Gbàgbé Rẹ̀?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Jèhófà, Ọlọ́run Tí “Ó Múra Àtidáríjì”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
w13 5/1 ojú ìwé 15

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Ǹjẹ́ Ọlọ́run lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá?

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 15]

Kò ṣòro láti rí ojú rere Ọlọ́run

Bíbélì fi hàn pé, gbogbo èèyàn ni ẹlẹ́ṣẹ̀. Látọ̀dọ̀ Ádámù ọkùnrin àkọ́kọ́, ni a ti jogún èròkérò tó máa ń mú ká dẹ́ṣẹ̀. Ìdí nìyẹn tó fi jẹ́ pé, nígbà míì a lè ṣe ohun tó burú, tí à á wá máa kábàámọ̀ rẹ̀ tó bá yá. Jésù Kristi, Ọmọ Ọlọ́run, kú nítorí tiwa, kó lè san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti jogún. Ẹbọ ìràpadà rẹ̀ ló mú ká lè máa rí ìdáríjì gbà. Ẹ̀bùn tí Ọlọ́run fún wa ni.—Ka Róòmù 3:23, 24.

Àwọn kan tó ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tó burú jáì máa ń wò ó pé bóyá ni Ọlọ́run lè dárí jì wọ́n. Àmọ́, ohun tí Ọ̀rọ̀ Ọlọrun sọ máa fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sọ pé: “Ẹ̀jẹ̀ Jésù Ọmọ rẹ̀ sì ń wẹ̀ wá mọ́ kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀.” (1 Jòhánù 1:7) Kódà, tí ẹ̀ṣẹ̀ tí a dá bá tiẹ̀ burú jáì, Jèhófà máa dárí jì wá pátápátá, tí a bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn.—Ka Aísáyà 1:18.

Kí ni a gbọ́dọ̀ ṣe kí Ọlọ́run tó lè dárí jì wá?

Tí a bá fẹ́ kí Jèhófà Ọlọ́run dárí jì wá, a ní láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀, ìyẹn ni pé ká lóye bó ṣe máa ń ṣe nǹkan, àwọn ìmọ̀ràn rẹ̀ àti àwọn ohun tó ń fẹ́ ká ṣe. (Jòhánù 17:3) Tayọ̀tayọ̀ ni Jèhófà máa ń dárí ji àwọn tó ronú pìwà dà, tí wọ́n kọ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì sapá láti yí ìwà wọn pa dà.—Ka Ìṣe 3:19.

Kò ṣòro láti rí ojú rere Ọlọ́run, torí pé Jèhófà mọ ibi tí a kù sí. Aláàánú àti onínúure ni. Ǹjẹ́ bí Jèhófà ṣe ń ṣàánú wa tìfẹ́tìfẹ́ mú kó wù ọ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa bí wàá ṣe máa ṣe ohun tó fẹ́?—Ka Sáàmù 103:13, 14.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́