ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w13 7/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìràpadà Ni Ẹ̀bùn Tó Dáa Jù Lọ Tí Ọlọ́run Fún Wa
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Ta Ni Jésù Kristi?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Ta Ni Jésù Kristi?
    Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run!
  • Jésù Ń gbani Là—Lọ́nà Wo?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
w13 7/1 ojú ìwé 16

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Ǹjẹ́ ó ṣeé ṣé kéèyàn wà láàyè títí láé?

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]

Kí la nílò ká tó lè bọ́ lọ́wọ́ ikú?

Ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún ni ọkùnrin àkọ́kọ́ náà, Ádámù lò láyé. Àmọ́ nígbà tó yá, ó darúgbó, ó sì kú. Láti ìgbà yẹn, oríṣiríṣi nǹkan ni àwọn èèyàn ń ṣe kí wọ́n má bàa darúgbó. Síbẹ̀, kò sí ẹni tó tíì rí oògùn ikú ṣe. Kí nìdí? Nígbà tí Ádámù ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run, ẹ̀ṣẹ̀ ló dá. Ìdí nìyẹn tó fi darúgbó tó sì kú. Torí náà, àwa náà ń darúgbó torí pé a ti jogún ẹ̀ṣẹ̀ látọ̀dọ̀ Ádámù, ikú sì ni èyí yọrí sí fún wa.—Ka Jẹ́nẹ́sísì 5:5; Róòmù 5:12.

Kí a tó lè máa wà láàyè títí láé, ẹni kan gbọ́dọ̀ san ìràpadà nítorí wa. (Jóòbù 33:24, 25) Ìràpadà ni iye tí èèyàn san láti dá ẹnì kan sílẹ̀ lómìnira. Nínú ọ̀ràn tiwa, a nílò òmìnira kúrò lọ́wọ́ ikú. (Ẹ́kísódù 21:29, 30) Jésù san ìràpadà yẹn nígbà tó kú fún wa.—Ka Jòhánù 3:16.

Kí ni èèyàn lè ṣe táá fi wà láàyè títí láé?

Kì í ṣe gbogbo èèyàn ló máa bọ́ lọ́wọ́ àìsàn àti ọjọ́ ogbó. Kódà, àwọn tó bá ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run bíi ti Ádámù, kò ní láǹfààní láti wà láàyè títí láé. Kìkì àwọn tí Ọlọ́run bá dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n nìkan ló máa wà láàyè títí láé.—Ka Aísáyà 33:24; 35:3-6.

Kí Ọlọ́run tó lè dárí jì wá, ohun kan wà tí a gbọ́dọ̀ ṣe. A gbọ́dọ̀ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ká lè mọ Ọlọ́run. Bíbélì jẹ́ ká mọ ohun tí a lè ṣe kí ayé wa lè dára, ó tún kọ́ wa bí a ṣe lè rí ojú rere Ọlọ́run àti ohun tí a máa ṣe ká lè wà láàyè títí láé.—Ka Jòhánù 17:3; Ìṣe 3:19.

Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i, ka orí 3 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́