ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 7/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Sísún Mọ́ Ọlọrun Nínú Àdúrà
    Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Àǹfààní Pàtàkì Ni Àdúrà Jẹ́
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Máa Gbàdúrà Kó O Lè Túbọ̀ Sún Mọ́ Ọlọ́run
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Sún Mọ́ Ọlọ́run Nípasẹ̀ Àdúrà
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 7/1 ojú ìwé 16

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa gbàdúrà?

Jèhófà Ọlọ́run fẹ́ ká máa sọ ohun tó wà lọ́kàn wa fún un ní fàlàlà àti nígbà gbogbo. (Lúùkù 18:1-7) Ó máa ń gbọ́ àdúrà wa nítorí ó nífẹ̀ẹ́ wa. Nígbà tó jẹ́ pé Jèhófà fúnra rẹ̀ ló ní ká máa bá òun sọ̀rọ̀, kí wá ló dé tá ò fi ní gbàdúrà sí i?—Ka Fílípì 4:6.

Kì í ṣe pé a fẹ́ béèrè fún ìrànlọ́wọ́ nìkan la ṣe ń gbàdúrà sí i, àmọ́, àdúrà máa ń jẹ́ ká sún mọ́ Ọlọ́run. (Sáàmù 8:3, 4) Tá a bá ń sọ ohun tó wà lọ́kàn wa fún Ọlọ́run nígbà gbogbo, ìyẹn á mú ká túbọ̀ di ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́.—Ka Jákọ́bù 4:8.

Báwo ló ṣe yẹ ká máa gbàdúrà?

Tá a bá ń gbàdúrà, Ọlọ́run ò fẹ́ ká máa fọ̀rọ̀ dárà tàbí ká máa gba àdúrà àkọ́sórí. Kò sì pọn dandan pé a gbọ́dọ̀ jókòó tàbí ká tẹrí ba, ká kúnlẹ̀ tàbí ká dúró ká tó lè gbàdúrà sí Ọlọ́run. Jèhófà ń fẹ́ ká sọ ohun tó wà lọ́kàn wa. (Mátíù 6:7) Bí àpẹẹrẹ, ní ilẹ̀ Ísírẹ́lì àtijọ́, Hánà gbàdúrà sí Jèhófà nípa ìṣòro tó ń bá a fínra nínú ìdílé rẹ̀. Kò pẹ́ tí ìbànújẹ́ rẹ̀ fi dayọ̀ tó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run látọkànwá nínú àdúrà rẹ̀.—Ka 1 Sámúẹ́lì 1:10, 12, 13, 26, 27; 2:1.

Ẹ ò rí i pé, àǹfààní aláìlẹ́gbẹ́ la ní láti sọ ohun tó jẹ́ ẹ̀dùn ọkàn wa fún Ẹlẹ́dàá! A tún lè yìn ín, bẹ́ẹ̀ ni a lè dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀ fún àwọn ohun tó ti ṣe fún wa. Ó dájú pé àwa gan-an mọyì irú àǹfààní aláìlẹ́gbẹ́ bẹ́ẹ̀.—Ka Sáàmù 145:14-16.

Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i, ka orí  17 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?, Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

Ó tún wà lórí ìkànnì www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́