ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 10/1 ojú ìwé 8-9
  • Ìjọba Ọlọ́run—Àǹfààní Wo Ló Máa Ṣe Ẹ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìjọba Ọlọ́run—Àǹfààní Wo Ló Máa Ṣe Ẹ́?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìjọba Ọlọ́run—Kí Nìdí Tó fi Ṣe Pàtàkì Gan-an sí Jésù?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Ìjọba Ọlọ́run
    Jí!—2013
  • Fi Hàn Nísinsìnyí Pé Ìjọba Ọlọ́run Lo Fara Mọ́!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 10/1 ojú ìwé 8-9

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ÌJỌBA ỌLỌ́RUN—ÀǸFÀÀNÍ WO LÓ MÁA ṢE Ẹ́?

Ìjọba Ọlọ́run—Àǹfààní Tó Máa Ṣe Ẹ́

Ó dájú pé ohun tó o kà nínú àwọn àkòrí méjì àkọ́kọ́ ti jẹ́ kó o mọ ìdí tí Ìjọba Ọlọ́run fi ṣe pàtàkì sí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Ṣé ìwọ náà ń fojú sọ́nà fún àwọn ìbùkún Ìjọba Ọlọ́run tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú, àbí ara ń fu ẹ́ pé àwọn ìlérí yẹn lè máà jóòótọ́?

Ọlọ́gbọ́n máa ń ní ìfura lóòótọ́, nítorí kì í ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ ló yẹ ká gbà gbọ́. (Òwe 14:15) Torí náà, tí ìwọ náà bá ń wádìí àwọn ohun tó o gbọ́ dáadáa, ńṣe lò ń fara wé àwọn ará Bèróà ìgbàanì.a Nígbà tí wọ́n kọ́kọ́ gbọ́ ìhìn rere nípa Ìjọba náà, wọ́n gbà á tọwọ́ tẹsẹ̀, àmọ́ wọ́n tún yiri ọ̀rọ̀ náà wò. Bíbélì tiẹ̀ sọ pé wọ́n fẹ̀sọ̀ ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ “ní ti pé bóyá bẹ́ẹ̀ ni nǹkan wọ̀nyí rí.” (Ìṣe 17:11) Lédè míì, ńṣe ni àwọn ará Bèróà fi ìhìn rere tí wọ́n gbọ́ wé ohun tó wà lákọọ́lẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́. Nígbẹ̀yìn, ó wá dá wọn lójú pé àtinú Bíbélì ni ìhìn rere tí àwọn gbọ́ ti wá.

Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà rọ̀ ẹ́ pé kí ìwọ náà ṣe bí àwọn ará Bèróà. A ṣe tán láti kọ́ ẹ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́fẹ̀ẹ́, o sì tún lè fi àwọn ohun tá a bá kọ́ ẹ nípa Ìjọba Ọlọ́run wé ohun tí Bíbélì fi kọ́ni ní ti gidi.

Ní àfikún sí ohun tó o bá kọ́ nípa Ìjọba Ọlọ́run, Bíbélì tún lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti rí ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè pàtàkì bí:

  • Ibo gan-an la ti wá?

  • Kí la wá ṣe láyé?

  • Kí nìdí tí Ọlọ́run fi fàyè gba ìjìyà?

  • Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sí wa nígbà tá a bá kú?

  • Ṣé ayé yìí máa pa rẹ́ lóòótọ́?

  • Kí ló lè mú kí ìdílé láyọ̀?

Àmọ́ ju gbogbo rẹ̀ lọ, ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì á jẹ́ kó o “sún mọ́ Ọlọ́run.” (Jákọ́bù 4:8) Àti pé, bó o ṣe ń sún mọ́ Ọlọ́run sí i, wàá túbọ̀ mọyì àwọn ohun rere tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe fún ẹ nísinsìnyí àti lọ́jọ́ iwájú. Ohun tí Jésù ní lọ́kàn nìyẹn nígbà tó gbàdúrà sí Baba rẹ̀ pé: “Èyí túmọ̀ sí ìyè àìnípẹ̀kun, gbígbà tí wọ́n bá ń gba ìmọ̀ ìwọ, Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà sínú, àti ti ẹni tí ìwọ rán jáde, Jésù Kristi.”—Jòhánù 17:3.

Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà lè lo ìwé yìí láti kó ẹ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.

Tó o bá fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́fẹ̀ẹ́, o lè kàn sí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tàbí kó o kọ ọ̀rọ̀ kún inú fọ́ọ̀mù tó wà lórí ìkànnì www.jw.org/yo. (Wo ìlujá tá a pè ní BÉÈRÈ ÌKẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ tó o wà ní ojúde ìkànnì náà)

a Bèróà jẹ́ ìlú kan ni Makedóníà àtijọ́.

Ọmọbìnrin kan Ṣàlàyé Bó Ṣe Fẹ́ràn Ìjọba Ọlọ́run Tó

Láìpẹ́ yìí ni ọmọbìnrin ọlọ́dún mẹ́wàá kan tó ń jẹ́ Fọlákẹ́ kọ àròkọ fún iléèwé rẹ̀ lórí àkòrí náà, “Ohun Tí Mo Fẹ́ràn Jù Láyé Yìí.” Fọlákẹ́ sọ ìdí tí òun fi fẹ́ràn láti máa sọ nípa Ìjọba Ọlọ́run fún àwọn èèyàn.

Fọlákẹ́ ṣàlàyé nínú àròkọ náà pé: “Ìjọba Ọlọ́run jẹ́ ìjọba gidi kan. Ṣùgbọ́n a kò lè fojú rí i, kódà tá a bá fi ìgò sójú pàápàá!”

Fọlákẹ́ tún sọ àwọn ìbùkún tó ń fojú sọ́nà fún, èyí tí Ìjọba Ọlọ́run máa mú wá. Ó mẹ́nu ba díẹ̀ lára àwọn ìṣòro tí Ìjọba náà máa fòpin sí, ó ní: “Inú mi máa ń bà jẹ́ tí mo bá rí àwọn èèyàn tó ń sun títì kiri àti ọ̀pọ̀ àwọn ọmọdé tí ebi ń pa kárí ayé. Ṣùgbọ́n mo máa ń láyọ̀ tí mo bá ka ìwé Aísáyà 65:21.” Ẹsẹ Bíbélì yẹn sọ ìlérí tí Ọlọ́run ṣe fún àwọn tó máa wà lábẹ́ ìṣàkóso Ìjọba rẹ̀, ó ní: “Dájúdájú, wọn yóò kọ́ ilé, wọn yóò sì máa gbé inú wọn; dájúdájú, wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì máa jẹ èso wọn.”

Fọlákẹ́ sọ pé òun ń retí ìgbà tí Ọlọ́run máa lo Ìjọba rẹ̀ láti mú gbogbo àìsàn kúrò. Ó fa ọ̀rọ̀ yọ látinú ìwé Ìṣípayá 21:4 nínú àròkọ rẹ̀, èyí tó sọ pé, Ọlọ́run yóò “nu omijé gbogbo nù kúrò ní ojú wọn, ikú kì yóò sì sí mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sí ọ̀fọ̀ tàbí igbe ẹkún tàbí ìrora mọ́.” Ó wá parí àròkọ rẹ̀ pé, “ohun tí mo fẹ́ràn jù láyé yìí ni kí n máa sọ̀rọ̀ nípa Jèhófà àti Ìjọba rẹ̀.” Láìfọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ, ọmọbìnrin yìí fi hàn lóòótọ́ pé Ìjọba Ọlọ́run ni òun fẹ́ràn jù!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́