ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 5/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ni Yóò Ṣẹlẹ̀ ní Ọjọ́ Ìdájọ́?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Kí Ni Ọjọ́ Ìdájọ́?
    Jí!—2010
  • Kí Ni Ọjọ́ Ìdájọ́?
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ọjọ Idajọ—Akoko Ireti Kan!
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 5/1 ojú ìwé 16

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Kí ni Ọjọ́ Ìdájọ́?

Àjíǹde mú kí ìdílé kan tún láyọ̀ padà nígbà ẹgbẹ̀rún ọdún náà

Kí nìdí tí ọjọ́ ìdájọ́ fi máa jẹ́ àkókò aláyọ̀?

Nígbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, Ọlọ́run lo àwọn onídàájọ́ láti gba àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìṣèdájọ́ òdodo. (Àwọn Onídàájọ́ 2:18) Bíbélì sọ pé ọjọ́ ayọ̀ ni ọjọ́ ìdájọ́ tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú yóò jẹ́, torí Jèhófà Onídàájọ́ gbogbo ilẹ̀ ayé máa gba aráyé là kúrò lọ́wọ́ àìsí ìdájọ́ òdodo.—Ka Sáàmù 96:12, 13; Aísáyà 26:9.

Ọlọ́run ti yan Jésù láti jẹ́ onídàájọ́ òdodo fún àwọn alààyè àti òkú. (Ìṣe 10:42; 17:31) Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti kú láìmọ̀ Ọlọ́run. Àmọ́, ní Ọjọ́ Ìdájọ́, Jésù máa jí àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ dìde kí wọ́n lè kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ọlọ́run tòótọ́ kí wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.—Ka Ìṣe 24:15.

Kí nìdí tí Ọjọ́ Ìdájọ́ fi máa gba ẹgbẹ̀rún ọdún?

Nígbà ẹgbẹ̀rún ọdún ni Jésù máa jí àwọn òkú dìde. (Ìṣípayá 20:4, 12) Wọ́n máa ní àkókò tó pọ̀ tó láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn ohun tí Ọlọ́run fẹ́, kí wọ́n sì ṣègbọràn sí i. Bíbélì fi hàn pé, ohun tí àwọn èèyàn yìí bá ṣe lẹ́yìn tí wọ́n bá jíǹde ni a ó fi ṣèdájọ́ wọn, èyí sì yàtọ̀ sí èrò ọ̀pọ̀ èèyàn.—Ka Róòmù 6:7.

Bíbélì tún sọ nípa ọjọ́ ìdájọ́ kan tó máa wáyé ṣáájú kí ẹgbẹ̀rún ọdún náà tó bẹ̀rẹ̀. Òjijì ni ìṣèlẹ̀ náà yóò sì wàyé. Gẹ́gẹ́ bá a ṣe sọ nínú àwọn àpilẹ̀kọ tó wà níbẹ̀rẹ̀ ìwé yìí, ọjọ́ yẹn ni à ń pè ní òpin. Lọ́jọ́ náà, Ọlọ́run máa mú gbogbo àwọn tí kò ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn èèyàn búburú kúrò. (2 Pétérù 3:7) Nígbà náà, a gbọ́dọ̀ sapá kí a ba lè fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run.—Ka 2 Pétérù 3:9, 13.

Fún ìsọfúnni síwájú sí i, wo ojú ìwé 213 nínú ìwé yìí. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

Ó tún wà lórí ìkànnì www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́