ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp16 No. 5 ojú ìwé 3
  • Gbogbo Wa La Nílò Ìtùnú

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbogbo Wa La Nílò Ìtùnú
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bá A Ṣe Lè Rí Ìtùnú Lásìkò Wàhálà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016
  • Tu Àwọn Tó Ń Ṣọ̀fọ̀ Nínú
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Bá A Ṣe Lè Pèsè Ìtùnú fún Àwọn Tí Wọ́n Bá Lò Pọ̀ Nígbà Tí Wọ́n Wà Lọ́mọdé (Apá Kẹrin Nínú Mẹ́rin)
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
  • Ìrẹ̀lẹ́kún Láti Ọ̀dọ̀ “Ọlọrun Ìtùnú Gbogbo”
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016
wp16 No. 5 ojú ìwé 3

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | IBO LO TI LÈ RÍ ÌTÙNÚ?

Gbogbo Wa La Nílò Ìtùnú

Ìyá kan tó ń tu ọmọ rẹ̀ nínú

Ṣé o rántí ìgbà kan tó o ṣubú ní kékeré? Bóyá tápá rẹ tiẹ̀ kán tàbí tó o fi ojúgun gbá. Ṣé o ṣì lè rántí bí ìyá rẹ ṣe rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún? Ó ṣeé ṣe kí màmá rẹ bá ẹ nu ojú ọgbẹ́ náà, kí wọ́n sì fi nǹkan dè é. Bó o ṣe ń ké ni wọ́n á máa kí ẹ pẹ̀lẹ́, tí wọ́n á sì máa gbá ẹ mọ́ra títí tọ́kàn rẹ á fi balẹ̀ pẹ̀sẹ̀. Nígbà yẹn, kò ṣòro fún ẹ láti rẹ́ni tù ẹ́ nínú.

Àmọ́ ńṣe ni gbogbo nǹkan ń le sí i bá a ṣe ń dàgbà. Bí ìṣòro ṣe ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ ló ṣe ń nira sí i láti rẹ́ni tù wá nínú. Ìṣòro táwọn ọ̀dọ́ ń bá fínra kọjá ká de ojú ọgbẹ́ àti ká gbáni mọ́ra lọ. Ẹ jẹ́ ká gbé àwọn àpẹẹrẹ díẹ̀ yẹ̀ wò.

  • Ǹjẹ́ iṣé ti bọ́ lọ́wọ́ rẹ rí? Julian sọ pé ńṣe lòun ń kanra lódìlódì nígbà tí iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ òun. Ó bẹ̀rẹ̀ sí í ronú pé: ‘Báwo ni máa ṣe tọ́jú ìdílé mi? Lẹ́yìn gbogbo ọdún tí mo fi ṣiṣẹ́ àṣekára ní ilé-iṣé yìí, kí ló dé tí wọ́n fi ronú pé mi ò wúlò fún àwọn mọ́?’

  • Lóòótọ́, ọkàn rẹ lè gbọgbẹ́ torí pé ìdílé rẹ ti tú ká. Raque sọ pé: “Nígbà tí ọkọ mi kàn ṣàdédé kúrò nílé ní oṣù méjìdínlógún [18] sẹ́yìn, ńṣe ló dà bíi pé wọ́n da aṣọ ìbànújẹ́ bò mí. Àfi bíi pé ọkàn mi ya sí méjì. Mò ń jẹ̀rora nínú lọ́hùn, ó sì ń hàn nínú gbogbo ohun tí mò ń ṣe. Ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn bà mí lẹ́rù gan-an.”

  • Ó lè jẹ́ àìsàn burúkú kan ló ń ṣe ẹ́ tí kò sì sí àmì pé ó máa lọ rárá. Láwọn ìgbà míì, ó lè máa ṣe ẹ́ bíi Jóòbù tó kérora pé: “Mo kọ̀ ọ́; èmi kì yóò wà láàyè fún àkókò tí ó lọ kánrin.” (Jóòbù 7:16) Luis tó jẹ́ ẹni ọgọ́rin [80] ọdún sọ bọ́rọ̀ náà ṣe rí lára rẹ̀, ó ní: “Nígbà míì, ó máa ń ṣe mí bíi pé kí n kú kíá jàre.”

  • Ó sì lè jẹ́ pé ikú ẹnì kan tó sún mọ́ ẹ ló ń mú kó o máa wá ìtùnú. Robert sọ pé: “Nígbà tí mo gbọ́ pé ọmọkùnrin mi kú nínú jàǹbá ọkọ̀ òfuurufú, ó kọ́kọ́ ṣe mí bíi pé irọ́ ni, kò pẹ́ sásìkò yẹn ni ọgbẹ́ ọkàn ńlá dé bá mi, irú èyí tí Bíbélì fi wé idà gígùn tó ń gúnni lọ́kàn.”​—Lúùkù 2:⁠35.

Robert, Luis, Raquel àti Julian rí ìtùnú gbà, kódà nínú ipò ìbànújẹ́ tí wọ́n wà yẹn. Wọ́n rí Ẹnì kan tó lè fún wọn ní ìtùnú ìyẹn Ọlọ́run Olódùmarè. Báwo ló ṣe ń tù wá nínú? Ǹjẹ́ ó máa tu ìwọ náà nínú?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́