ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/99 ojú ìwé 1
  • Máa Gbàdúrà fún Ìrànlọ́wọ́ Jèhófà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Gbàdúrà fún Ìrànlọ́wọ́ Jèhófà
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ Sọ Ẹ̀dùn Ọkàn Yín Fún Ọlọ́run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
  • Kí Ni Àdúrà Rẹ Ń Sọ Nípa Rẹ?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Mọyì Àǹfààní Tó O Ní Láti Máa Gbàdúrà sí Ọlọ́run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
  • Bó O Ṣe Lè Mú Kí Àdúrà Ẹ Sunwọ̀n Sí I
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
km 7/99 ojú ìwé 1

Máa Gbàdúrà fún Ìrànlọ́wọ́ Jèhófà

1 Jésù tẹ̀ ẹ́ mọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ lọ́kàn pé wọ́n nílò ìbùkún Jèhófà nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ wọn. (Mát. 9:37, 38) Àdúrà ìyìn àti ìdúpẹ́ àtọkànwá, pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn ìbéèrè àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ àtinúwá wa ń fi hàn pé a gbára lé Jèhófà pátápátá fún ìrànlọ́wọ́ rẹ̀. (Fílí. 4:6, 7) Ìwé Mímọ́ rọ̀ wá pé kí a máa gba “gbogbo oríṣi àdúrà àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀,” èyí sì kan àwọn àdúrà táa ń gbà nípa iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà.—Éfé. 6:18.

2 A ń yin Jèhófà nínú àdúrà wa nítorí àwọn ànímọ́ àti àṣeyọrí rẹ̀ aláìlẹ́gbẹ́. A tún ń yìn ín gẹ́gẹ́ bí Olùfúnni ní ìhìn rere táa ń wàásù. Ó yẹ ká máa yìn ín torí pé òun nìkan ló ń mú kí iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa kẹ́sẹ járí.—Sm. 127:1.

3 Àdúrà ìdúpẹ́ wa ń fi ìmọrírì hàn fún òye tí Jèhófà ti fún wa nípa ìfẹ́ àti ète rẹ̀. Kì í ha ṣe àǹfààní ló jẹ́ láti ṣàjọpín òtítọ́ Ìjọba náà pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn? A dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà fún gbogbo ohun tí à ń gbé ṣe nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà.—Sm. 107:8; Éfé. 5:20.

4 Lọ́nà tó bá a mu gẹ́ẹ́, a máa ń béèrè fún ìrànlọ́wọ́ Jèhófà láti rí àwọn èèyàn tí yóò tẹ́wọ́ gba ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì táa fi ń lọ̀ wọ́n, a sì ń béèrè fún ìrànlọ́wọ́ kí a lè mú òtítọ́ dé inú ọkàn-àyà wọn. Nípa bíbéèrè irú ìbéèrè bẹ́ẹ̀, a ń fi hàn pé a gbà pé Ọlọ́run nìkan ló lè mú kí iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa sèso.—1 Kọ́r. 3:5-7.

5 Arábìnrin kan nímọ̀lára pé obìnrin kan tí ń bẹ ní ipa ọ̀nà ìwé ìròyìn òun kì í ka Ilé Ìṣọ́ àti Jí! Níwọ̀n bí kò ti fẹ́ káwọn ìwé ìròyìn ṣíṣeyebíye wọ̀nyí di àkódànù, ó bẹ Jèhófà pé bí obìnrin náà kì í báá kà wọ́n, kí ó kọ̀ láti gbà wọ́n. Nígbà tí arábìnrin náà padà débẹ̀, ọkọ obìnrin náà sọ pé: “O ṣeun fún mímú ìwé ìròyìn wọ̀nyí wá déédéé. Mò ń kà wọ́n, mo si fẹ́ràn wọn gan-an ni.”

6 Pẹ̀lú àrọwà tó fẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ hàn tó sì jẹ́ àtinúwá, a lè rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Jèhófà pé kí ó ràn wá lọ́wọ́ láti kojú ìwà àgunlá àti ìṣáátá tí àwọn èèyàn ń hù, kí a sì borí ìbẹ̀rù ènìyàn, kí ó lè ṣeé ṣe fún wa láti máa fi àìṣojo wàásù fáwọn ẹlòmíràn. (Ìṣe 4:31) Bí a bá ń bá a nìṣó láti máa gba “gbogbo oríṣi àdúrà àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀” bí a ti ń fi tìgbọràn-tìgbọràn ṣe iṣẹ́ ìsìn ọlọ́wọ̀ wa nìṣó, ìdánilójú wà pé Jèhófà yóò ràn wá lọ́wọ́.—1 Jòh. 3:22.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́