ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/02 ojú ìwé 1
  • Àwọn Èèyàn Tó Jẹ́ Aláyọ̀ Jù Lọ Lórí Ilẹ̀ Ayé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Èèyàn Tó Jẹ́ Aláyọ̀ Jù Lọ Lórí Ilẹ̀ Ayé
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Aláyọ̀ Ni Àwọn Tó Ń Sin “Ọlọ́run Aláyọ̀”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • O Lè Ní Ayọ̀ Tòótọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
  • Bí A Ṣe Lè Láyọ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Ayọ Tootọ Ninu Ṣiṣiṣẹsin Jehofa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
km 8/02 ojú ìwé 1

Àwọn Èèyàn Tó Jẹ́ Aláyọ̀ Jù Lọ Lórí Ilẹ̀ Ayé

1 “Aláyọ̀ ni àwọn ènìyàn tí Jèhófà jẹ́ Ọlọ́run wọn!” (Sm. 144:15) Àwọn ọ̀rọ̀ yẹn fi àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà hàn gẹ́gẹ́ bí àwọn èèyàn tó láyọ̀ jù lọ lórí ilẹ̀ ayé. Kò sí ayọ̀ kankan tó ju ayọ̀ tó ń wá látinú sísin Jèhófà, Ọlọ́run tòótọ́ àti Ọlọ́run alààyè kan ṣoṣo náà. Níwọ̀n bí ó ti jẹ́ “Ọlọ́run aláyọ̀,” àwọn tó ń sìn ín ń gbé ìdùnnú rẹ̀ yọ. (1 Tím. 1:11) Kí ni díẹ̀ lára àwọn apá ìjọsìn wa tó ń mú ká jẹ́ aláyọ̀ gan-an?

2 Àwọn Ohun Tó Ń Mú Ká Jẹ́ Aláyọ̀: Jésù mu dá wa lójú pé, ayọ̀ máa ń wá látinú jíjẹ́ kí ‘àìní wa nípa ti ẹ̀mí máa jẹ wá lọ́kàn.’ (Mát. 5:3) Kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nígbà gbogbo àti wíwá sí gbogbo àwọn ìpàdé Kristẹni la fi ń bójú tó àìní yẹn. Mímọ òtítọ́ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ti sọ wá dòmìnira kúrò nínú ìsìn èké àtàwọn ìṣìnà tó kúnnú rẹ̀. (Jòh. 8:32) Ìwé Mímọ́ tún ti kọ́ wa ní ọ̀nà tó dára jù lọ láti gbà gbé ìgbésí ayé. (Aísá. 48:17) Fún ìdí yìí, à ń gbádùn ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ Kristẹni tó gbámúṣé láàárín àwọn ẹgbẹ́ ará wa tó jẹ́ aláyọ̀.—1 Tẹs. 2:19, 20; 1 Pét. 2:17.

3 À ń rí ìtẹ́lọ́rùn tó ga nínú ṣíṣègbọràn sí àwọn ìlànà ìwà rere gíga ti Ọlọ́run, níwọ̀n bí a ti mọ̀ pé èyí ń dáàbò bò wá ó sì ń mú Jèhófà láyọ̀. (Òwe 27:11) Akọ̀ròyìn kan sọ pé: “Laika awọn ọpa idiwọn wọn ti ko gba gbẹ̀rẹ́ si, awọn Ẹlẹrii Jehofah ko farahan [bi] alailayọ. Odikeji ni. Awọn ọ̀dọ́ ati agba [to wa laaarin wọn] a maa fi irisi lilayọ ati wiwa ni iwọntun-wọnsi li ọna ara-ọ̀tọ̀ hàn.” Báwo la ṣe lè ran àwọn mìíràn lọ́wọ́ káwọn náà bàa lè gbé irú ìgbésí aláyọ̀ tí à ń gbé?

4 Ran Àwọn Mìíràn Lọ́wọ́ Láti Rí Ayọ̀: Ìbànújẹ́ ló kúnnú ayé fọ́fọ́, ńṣe ni ọjọ́ iwájú sì pòkúdu fún àwọn èèyàn ní gbogbo gbòò. Àmọ́ ṣá o, pẹ̀lú ayọ̀ la fi ń wo ọjọ́ iwájú, nítorí a mọ̀ pé lọ́jọ́ kan, gbogbo ohun tó ń fa ìbànújẹ́ pátá ló máa di ohun ìgbàgbé. (Ìṣí. 21:3, 4) Nípa bẹ́ẹ̀, tìtaratìtara la fi ń kópa nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà, tí à ń wá àwọn olóòótọ́ ọkàn láti bàa lè sọ fún wọn nípa ìrètí wa àtàwọn ohun tá a gbà gbọ́ nípa Jèhófà.—Ìsík. 9:4.

5 Arábìnrin kan tó jẹ́ aṣáájú ọ̀nà sọ pé: “Kò sí ohun kan tí ń mú ìtẹ́lọ́rùn wá ju ríran àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti mọ Jèhófà àti òtítọ́ rẹ̀.” Ẹ jẹ́ ká ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti ran ọ̀pọ̀ èèyàn sí i lọ́wọ́ láti tẹ́wọ́ gba ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé. Ṣíṣiṣẹ́sin Jèhófà àti lílo ara wa nínú ríran àwọn ẹlòmíràn lọ́wọ́ láti sìn ín ń mú ayọ̀ tó ga lọ́lá wá.—Ìṣe 20:35.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́