May 9 Sí 15
SÁÀMÙ 1-10
Orin 99 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Tá A Bá Fẹ́ Wà Ní Àlááfíà Pẹ̀lú Jèhófà, A Ní Láti Bọ̀wọ̀ fún Jésù Ọmọ Rẹ̀”: (10 min.)
[Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò tá a pe àkọlé rẹ̀ ní Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sáàmù.]
Sm 2:1-3—Bíbélì sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn alákòóso máa kórìíra Jèhófà àti Jésù (w04 7/15 ojú ìwé 16 àti 17 ìpínrọ̀ 4 sí 8; it-1-E ojú ìwé 507; it-2-E ojú ìwé 386 ìpínrọ̀ 3)
Sm 2:8-12—Awọn tó bá bọ̀wọ̀ fún Ọba tí Jèhófà fòróró yàn nìkan ni yóò ní ìyè (w04 8/1 ojú ìwé 5 ìpínrọ̀ 2 àti 3)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Sm 2:7—Kí ni “àṣẹ àgbékalẹ̀ Jèhófà”? (w06 5/15 ojú ìwé 17 ìpínrọ̀ 6)
Sm 3:2—Kí ni ọ̀rọ̀ náà Sélà túmọ̀ sí? (w06 5/15 ojú ìwé 18 ìpínrọ̀ 2)
Ẹ̀kọ́ wo ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ mi nípa Jèhófà?
Àwọn kókó wo látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí ni mo lè lò lóde ẹ̀rí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Sáàmù 8:1–9:10
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Nígbà Àkọ́kọ́: (2 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Àwòrán iwájú ìwé ìròyìn wp16.3—Ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan fún onílé lórí fóònú tàbí tablet rẹ.
Ìpadàbẹ̀wò: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Àwòrán iwájú ìwé ìròyìn wp16.3—Kí onílé sọ pé òun ò fẹ́ kó o ka Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, kó o wá ka ìtumọ̀ Bíbélì míì lórí JW Library.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì: (6 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) bh ojú ìwé 12 ìpínrọ̀ 12 àti 13—Gba ẹni tí ò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ níyànjú pé kó fi JW Library sórí fóònú tàbí tablet rẹ̀.
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Máa Bọ̀wọ̀ fún Ilé Jèhófà: (5 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò tó wà lórí ìkànnì jw.org/yo tá a pè ní Di Ọ̀rẹ́ Jèhófà—Máa Bọ̀wọ̀ fún Ilé Jèhófà. (Lọ sí Ẹ̀KỌ́ BÍBÉLÌ > ÀWỌN ỌMỌDÉ.) Lẹ́yìn náà, pe àwọn ọmọdé wá sórí pèpéle, kó o sì bi wọ́n láwọn ìbéèrè díẹ̀ nípa fídíò náà.
Orúkọ Ọlọ́run Nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù: (10 min.) Àsọyé tó dá lórí apá 1 nínú ìwé Àfikún Ìsọfúnni Láti Lóye Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) ia orí 15 ìpínrọ̀ 1 sí 14 àti àpótí tó wà lójú ìwé 138
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 11 àti Àdúrà