July 3-9
Ìsíkíẹ́lì 11-14
Orin 52 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Ṣé O Máa Ń Jẹ́ Kí Jèhófà Tọ́ Ẹ Sọ́nà?”: (10 min.)
Isk 11:17, 18—Jèhófà ṣèlérí pé òun máa mú ìjọsìn tòótọ́ pa dà bọ̀ sípò (w07 7/1 11 ¶4)
Isk 11:19—Jèhófà lè jẹ́ ká túbọ̀ máa fòye mọ àwọn ohun tó fẹ́ ká ṣe (w16.05 15 ¶9)
Isk 11:20—Jèhófà fẹ́ ká máa fi ohun tí à ń kọ́ sílò
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Isk 12:26-28—Kí ni àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí sọ pé àwa ìránṣẹ́ Jèhófà ní láti ṣe? (w07 7/1 13 ¶8)
Isk 14:13, 14—Kí la rí kọ́ nínú bá a ṣe dárúkọ àwọn tó wà nínú ẹsẹ Bíbélì yìí? (w16.05 26 ¶13; w07 7/1 13 ¶9)
Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà?
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Isk 12:1-10
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Múra Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Oṣù Yìí Sílẹ̀: (15 min.) Ìjíròrò tó dá lórí “Àwọn Ọ̀nà Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Tá A Lè Lò.” Jẹ́ kí àwọn ará wo ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn fídíò ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀, kẹ́ ẹ sì jíròrò àwọn kókó pàtàkì látinú àwọn fídíò náà.
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Ohun tó ń fẹ́ àbójútó nínú ìjọ: (15 min.) Tàbí kẹ́ ẹ jíròrò ohun tẹ́ ẹ kọ́ nínú Ìwé Ọdọọdún. (yb17 41-43)
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) kr orí 14 ¶15-23, àpótí “Ṣé O Gbà Lóòótọ́ Pé Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso?”
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 43 àti Àdúrà