July 17-23
Ìsíkíẹ́lì 18-20
Orin 21 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Tí Jèhófà Bá Ti Dárí Ẹ̀ṣẹ̀ Jini, Ṣé Ó Máa Ń Gbàgbé Rẹ̀?”: (10 min.)
Isk 18:19, 20—Kálukú ló máa jíhìn ohun tó bá yàn láti ṣe (w12 7/1 18 ¶2)
Isk 18:21, 22—Tí Jèhófà bá ti dárí ẹ̀ṣẹ̀ jini kò ní ka ẹ̀ṣẹ̀ yẹn sí wa lọ́rùn mọ́ lọ́jọ́ iwájú (w12 7/1 18 ¶3-7)
Isk 18:23, 32—Tí àwọn ẹni ibi bá kọ̀ láti ronú pìwà dà, ìgbà yẹn ni Jèhófà máa ń tó pa wọ́n run (w08 4/1 8 ¶4; w06 12/1 27 ¶11)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.)
Isk 18:29—Kí nìdí tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ní èrò tí kò tọ́ nípa Jèhófà, báwo ni àwa náà kò ṣe ní ṣe irú àṣìṣe kan náà? (w13 8/15 11 ¶9)
Isk 20:49—Kí nìdí tí àwọn èèyàn náà fi rò pé “ọ̀rọ̀ òwe,” ni Ìsíkíẹ́lì ń bá àwọn sọ, báwo ni ìyẹn ṣe jẹ́ ìkìlọ̀ fún wa? (w07 7/1 14 ¶3)
Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà?
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Isk 20:1-12
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Nígbà Àkọ́kọ́: (2 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) 1Jo 5:19 —Máa Fi Òtítọ́ Kọ́ni. Jẹ́ kí onílé mọ̀ pé o máa pa dà wá.
Ìpadàbẹ̀wò: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Jẹ 3:2-5—Máa Fi Òtítọ́ Kọ́ni. Jẹ́ kí onílé mọ̀ pé o máa pa dà wá. (Wo mwb16.08 8 ¶2.)
Àsọyé: (6 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) w16.05 32—Àkòrí: Báwo Ni Àwọn Ará Nínú Ìjọ Ṣe Lè Fi Ayọ̀ Wọn Hàn Nígbà Tí Wọ́n Bá Ṣèfilọ̀ Pé A Ti Gba Ẹnì Kan Tá A Yọ Lẹ́gbẹ́ Pa Dà?
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
“Ṣé O Máa Ń Dárí Ji Ara Rẹ?”: (10 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará kọ́kọ́ wo fídíò náà, Máa Fi Ìdúróṣinṣin Ti Àwọn Ìdájọ́ Jèhófà Lẹ́yìn—Máa Dárí Jini.
Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé—Kí Ló Yẹ Kí N Ṣe Tí Mo Bá Ṣàṣìṣe?: (5 min.) Ẹ jíròrò àpilẹ̀kọ náà “Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé—Kí Ló Yẹ Kí N Ṣe Tí Mo Bá Ṣàṣìṣe?” èyí tó wà nínú ìwé pẹlẹbẹ Ìdáhùn Àwọn Ìbéèrè 10 Táwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè. Jẹ́ kí àwọn ará kọ́kọ́ gbọ́ ohùn tá a gbà sílẹ̀ náà, èyí tó bẹ̀rẹ̀ láti “Kí Lo Máa Ṣe?”
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) kr orí 15 ¶9-17
Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.)
Orin 38 àti Àdúrà