ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 June ojú ìwé 3
  • June 8-14

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • June 8-14
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 June ojú ìwé 3

June 8-14

JẸ́NẸ́SÍSÌ 46-47

  • Orin 86 àti Àdúrà

  • Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

  • “Jèhófà Pèsè Oúnjẹ Lásìkò Ìyàn”: (10 min.)

    • Jẹ 47:13​—Ìyàn mú gan-an nílẹ̀ Íjíbítì àti ilẹ̀ Kénáánì (w87 5/1 15 ¶2)

    • Jẹ 47:16, 19, 20​—Àwọn ará Íjíbítì yááfì ọ̀pọ̀ nǹkan kí wọ́n má bàa kú

    • Jẹ 47:23-25​—Ó gba ìsapá ká tó lè jàǹfààní látinú ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ oúnjẹ tẹ̀mí tí ètò Ọlọ́run ń pèsè fún wa lónìí (kr 235 ¶11-12)

  • Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (10 min.)

    • Jẹ 46:4​—Kí ni Jèhófà ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé Jósẹ́fù yóò “gbé ọwọ́ rẹ̀ lé” ojú Jékọ́bù? (it-1 220 ¶1)

    • Jẹ 46:26, 27​—Èèyàn mélòó nínú ìdílé Jékọ́bù ló bá a lọ sí Íjíbítì? (“gbogbo wọn lápapọ̀ jẹ́ márùndínlọ́gọ́rin (75)” àlàyé ọ̀rọ̀ lórí Iṣe 7:14, nwtsty)

    • Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí nípa Jèhófà, iṣẹ́ ìwàásù tàbí àwọn nǹkan míì?

  • Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Jẹ 47:1-17 (th ẹ̀kọ́ 10)

MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

  • Fídíò Nígbà Àkọ́kọ́: (4 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà, lẹ́yìn náà béèrè àwọn ìbéèrè yìí: Báwo ni akéde yẹn ṣe lo ìbéèrè lọ́nà tó gbéṣẹ́? Báwo ló ṣe ṣàlàyé ẹsẹ Bíbélì tó kà?

  • Nígbà Àkọ́kọ́: (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. Lẹ́yìn náà, fún un ní ọ̀kan lára àwọn ìtẹ̀jáde tó wà nínú Àpótí Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́. (th ẹ̀kọ́ 3)

  • Nígbà Àkọ́kọ́: (5 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. Lẹ́yìn náà, fún un ní ìwé Bíbélì Kọ́ Wa, kó o sì bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ní orí 9. (th ẹ̀kọ́ 14)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

  • Orin 96

  • Máa Fiyè Sí Àwọn Ìránnilétí Jèhófà: (15 min.) Ẹ wo fídíò Mọyì Àwọn Ìránnilétí Jèhófà. Rọ àwọn ará pé kí wọ́n máa ka Bíbélì déédéé, kí wọ́n sì máa gbádùn gbogbo oúnjẹ tẹ̀mí tí ètò Ọlọ́run ń pèsè.​—Ais 25:6; 55:1; 65:13; Mt 24:45.

  • Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) jy orí 118

  • Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)

  • Orin 109 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́