ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb24 January ojú ìwé 6-7
  • January 22-28

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • January 22-28
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
mwb24 January ojú ìwé 6-7

JANUARY 22-28

JÓÒBÙ 38-39

Orin 11 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ṣé O Máa Ń Wáyè Kíyè sí Àwọn Ohun Tí Ọlọ́run Dá?

(10 min.)

Lẹ́yìn tí Jèhófà dá ayé yìí, ó lo àkókò láti yẹ ohun tó ṣe wò (Jẹ 1:10, 12; Job 38:5, 6; w21.08 9 ¶7)

Àwọn áńgẹ́lì fara balẹ̀ wo ohun tí Jèhófà dá (Job 38:7; w20.08 14 ¶2)

Táwa náà bá ń wáyè kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà dá tá a sì mọyì rẹ̀, ìgbàgbọ́ wa máa lágbára sí i (Job 38:32-35; w23.03 17 ¶8)

Inú ìyá kan àti ọmọ ẹ̀ ń dún bí wọ́n ṣe ń wo labalábá kan níwájú ilé wọn.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Job 38:8-10—Kí ni àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí kọ́ wa nípa àwọn òfin tí Jèhófà fún wa? (it-2 222)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Job 39:1-22 (th ẹ̀kọ́ 5)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(2 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Fi ọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ parí ọ̀rọ̀ ẹ nígbà tó o kíyè sí i pé kò wu ẹni náà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 3)

5. Pa Dà Lọ

(5 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Nígbà tẹ́ ẹ jọ sọ̀rọ̀ kẹ́yìn, ẹni náà sọ fún ẹ pé èèyàn òun kan kú lẹ́nu àìpẹ́ yìí. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 3)

6. Àsọyé

(5 min.) lmd àfikún A kókó 1—Àkòrí: Àwọn Nǹkan Tó Ń Ṣẹlẹ̀ Kárí Ayé àti Ìwà Àwọn Èèyàn Fi Hàn Pé Nǹkan Máa Tó Yí Pa Dà. (th ẹ̀kọ́ 16)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 111

7. Àwọn Ohun Tí Jèhófà Dá Máa Ń Jẹ́ Ká Rántí Àwọn Ohun Tó Ṣe Pàtàkì

(15 min.) Ìjíròrò.

Jóòbù ń ronú nípa àwọn ẹranko tó jẹ́ àgbàyanu tí Jèhófà dá, lára wọn ni erinmi, ẹyẹ àkọ̀, ògòǹgò, ọ̀nì, idì, ẹṣin àti akọ màlúù. Ìjì ń jà, Élíhù àtàwọn olùtùnú èké mẹ́ta náà sì jókòó sítòsí.

Nígbà tí Sátánì fojú pọ́n Jóòbù táwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì sọ̀rọ̀ tí ò dáa sí i, àwọn ìṣòro tó dé bá Jóòbù ló gbà á lọ́kàn.

Ka Jóòbù 37:14. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

Kí ló yẹ kí Jóòbù ṣe kó lè máa ronú lọ́nà tó tọ́?

Tá a bá ń fara balẹ̀ kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà dá nígbà tá a bá wà nínú ìṣòro, ó máa jẹ́ ká rí bí Jèhófà ṣe lágbára tó, ìyẹn á sì jẹ́ kó máa wù wá láti jẹ́ olóòótọ́ sí i, ká sì túbọ̀ nígbàgbọ́ pé ó máa bójú tó wa.—Mt 6:26.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Ohun Tí Ìwé Jóòbù Kọ́ Wa—Àwọn Ẹranko. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

Kí lo rí nínú fídíò yìí tó lè mú kó o túbọ̀ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà?

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 4 ¶13-20

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 54 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́