ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb24 March ojú ìwé 5
  • March 18-24

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • March 18-24
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
mwb24 March ojú ìwé 5

MARCH 18-24

SÁÀMÙ 19-21

Orin 6 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

Arákùnrin kan ń wo ìràwọ̀ lójú òfúrufú.

1. “Àwọn Ọ̀run Ń Polongo Ògo Ọlọ́run”

(10 min.)

Àwọn ohun tí Jèhófà dá ń kéde ògo rẹ̀ (Sm 19:1; w04 1/1 8 ¶1-2)

Oòrùn jẹ́ ọ̀kan lára àwọn iṣẹ́ Jèhófà tó jẹ́ àgbàyanu (Sm 19:4-6; w04 6/1 11 ¶8-10)

Ó yẹ ká máa kẹ́kọ̀ọ́ lára àwọn ohun tí Jèhófà dá (Mt 6:28; g95 11/8 7 ¶3)

OHUN TẸ́ Ẹ LÈ ṢE NÍGBÀ ÌJỌSÌN ÌDÍLÉ: Ẹ kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà dá, kẹ́ ẹ sì jíròrò ohun tí wọ́n kọ́ yín nípa Jèhófà.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 19:7-9—Irú ewì wo ló wà nínú àwọn ẹsẹ yìí? (it-1 1073)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sm 19:1-14 (th ẹ̀kọ́ 11)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ NÍBI TÍ ÈRÒ PỌ̀ SÍ. Fún ẹnì kan ní ìwé tá a fi ń pe èèyàn sí Ìrántí Ikú Kristi, wo ibi tí wọ́n ti máa ṣe Ìrántí Ikú Kristi lágbègbè ẹni náà lórí jw.org. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 3)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Ẹnì kan sọ fún ẹ pé òun rí ìwé tá a fi ń pe àwọn èèyàn lẹ́nu ọ̀nà òun ló jẹ́ kóun wá sí Ìrántí Ikú Kristi. Kí ẹni náà tọ̀yàyàtọ̀yàyà, kó o sì ṣètò bó o ṣe máa dáhùn àwọn ìbéèrè ẹ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 3 kókó 4)

6. Ṣàlàyé Ohun Tó O Gbà Gbọ́

(5 min.) Àsọyé. ijwfq 45—Àkòrí: Kí Nìdí Tí Ọ̀nà Tí Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Gbà Ń Ṣe Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa Fi Yàtọ̀ sí Ti Àwọn Ẹlẹ́sìn Tó Kù? (th ẹ̀kọ́ 6)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 141

7. Jẹ́ Kí Àwọn Ohun Tí Jèhófà Dá Mú Kí Ìgbàgbọ́ Rẹ Lágbára Sí I

(15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ náà. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

Àwọn nǹkan wo lo rí nínú fídíò yìí tó mú kí ìgbàgbọ́ rẹ nínú Ẹlẹ́dàá lágbára sí i?

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 7 ¶9-13, àpótí ojú ìwé 56

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 127 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́