ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb24 March ojú ìwé 9-16
  • April 1-7

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • April 1-7
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
mwb24 March ojú ìwé 9-16

APRIL 1-7

SÁÀMÙ 23-25

Orin 4 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. “Jèhófà Ni Olùṣọ́ Àgùntàn Mi”

(10 min.)

Jèhófà ń darí wa (Sm 23:1-3; w11 5/1 31 ¶3)

Jèhófà ń dáàbò bò wá (Sm 23:4; w11 5/1 31 ¶4)

Jèhófà ń bọ́ wa (Sm 23:5; w11 5/1 31 ¶5)

Olùṣọ́ àgùntàn kan gbé ọ̀dọ́ àgùntàn kan mọ́ra, ó ń fọwọ́ pa á lára.

Bí olùṣọ́ àgùntàn onífẹ̀ẹ́ kan ṣe ń bójú tó àwọn àgùntàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Jèhófà ń bójú tó àwa ìránṣẹ́ rẹ̀.

BI ARA RẸ PÉ, ‘Àwọn nǹkan wo ni Jèhófà ti ṣe fún mi tó mú kí n gbà pé ó ń bójú tó mi?’

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 23:3—Kí ni “ipa ọ̀nà òdodo,” kí la lè ṣe tá ò fi ní kúrò ní ipa ọ̀nà yìí? (w11 2/15 24 ¶1-3)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sm 23:1–24:10 (th ẹ̀kọ́ 5)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Ẹni náà sọ pé inú òun ò dùn sí báwọn èèyàn ṣe ń ba àyíká jẹ́. Ka ẹsẹ Bíbélì kan táá fi í lókàn balẹ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

5. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Ṣàlàyé bá a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì fún ẹni tó gba ìwé Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìbẹ̀rẹ̀ Ẹ̀kọ́ Bíbélì. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 3)

6. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(5 min.) lff ẹ̀kọ́ 14 kókó 4 (lmd ẹ̀kọ́ 11 kókó 3)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 54

7. Má Ṣe Fetí sí Ohùn Àwọn Àjèjì

(15 min.) Ìjíròrò.

Olùṣọ́ àgùntàn kan àti àjèjì kan ń pe àwọn àgùntàn nígbà kan náà. Àwọn àgùntàn náà gbọ́ ohùn olùṣọ́ àgùntàn, wọ́n sì tẹ̀ lé e.

Àwọn àgùntàn mọ ohùn olùṣọ́ àgùntàn wọn, wọ́n sì máa ń tẹ̀ lé e. Àmọ́, wọ́n máa ń sá fún àjèjì torí wọn ò mọ ohùn rẹ̀. (Jo 10:5) Lọ́nà kan náà, a máa ń fetí sí ohùn àwọn Olùṣọ́ Àgùntàn wa, ìyẹn Jèhófà àti Jésù torí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ wa, wọ́n sì ṣeé fọkàn tán. (Sm 23:1; Jo 10:11) Àmọ́, a kì í fetí sí ohùn àwọn àjèjì tí wọ́n lè fi “ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn” ba ìgbàgbọ́ wa jẹ́.—2Pe 2:1, 3.

Jẹ́nẹ́sísì orí kẹta jẹ́ ká mọ ìgbà àkọ́kọ́ tá a gbọ́ ohùn àjèjì láyé. Sátánì ò jẹ́ kí Éfà mọ irú ẹni tóun jẹ́ nígbà tó yọ sí i. Ó ṣe bí ọ̀rẹ́ sí Éfà, ó sì parọ́ fún un pé Jèhófà ò ní ire ẹ̀ lọ́kàn. Ó bani nínú jẹ́ pé Éfà tẹ́tí sí ohùn àjèjì yìí, èyí sì kóyà jẹ òun àtàwọn àtọmọdọ́mọ rẹ̀.

Lónìí, Ṣátánì máa ń mú káwọn èèyàn parọ́ tàbí kí wọ́n sọ ọ̀rọ̀ àìdáa nípa Jèhófà àti ètò rẹ̀, ká lè bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiyèméjì. Tá a bá gbọ́ ohùn àjèjì, kí ló yẹ ká ṣe? Ó yẹ ká sá tèfètèfè! Ó máa léwu gan-an tá a bá lọ tẹ́tí sí wọn kódà kó jẹ́ fún ìgbà díẹ̀ torí pé a fẹ́ ṣe ojúmìító. Ká rántí pé ìwọ̀nba ọ̀rọ̀ díẹ̀ ni Sátánì fi tan Éfà jẹ. (Jẹ 3:1, 4, 5) Àmọ́, tó bá jẹ́ pé ẹnì kan tá a mọ̀, tó nífẹ̀ẹ́ wa, tó sì ní ire wa lọ́kàn ló fẹ́ sọ ohun tí ò dáa nípa ètò Ọlọ́run ńkọ́, kí la máa ṣe?

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Yẹra fún “Ohùn Àwọn Àjèjì.” Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

Kí lo kọ́ nínú ohun tí Jade ṣe nígbà tí ìyá rẹ̀ tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà fẹ́ sọ ohun tí ò dáa nípa ètò Ọlọ́run?

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 8 ¶1-4, àwọn àpótí ojú ìwé 61-62

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 55 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́