ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb25 May ojú ìwé 4-5
  • May 12-18

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • May 12-18
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
mwb25 May ojú ìwé 4-5

MAY 12-18

ÒWE 13

Orin 34 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Má Ṣe Jẹ́ Kí “Fìtílà Àwọn Ẹni Burúkú” Tàn Ẹ́ Jẹ

(10 min.)

Àwọn èèyàn burúkú ò nírètí ọjọ́ iwájú (Owe 13:9; it-2 196 ¶2-3)

Yẹra fún àwọn tó ń fi nǹkan búburú ṣayọ̀ (Owe 13:20; w12 7/15 12 ¶3)

Jèhófà máa ń bù kún àwọn olódodo (Owe 13:25; w04 7/15 31 ¶6)

Àwòrán: Ìyàtọ̀ tó wà nínú ìpinnu tí kò dáa tí ọkùnrin kan tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe àtàwọn ìpinnu tó dáa tí àwọn arákùnrin méjì ṣe. 1. Ọkùnrin kan ń jó níbi tí wọ́n ti ń ṣe fàájì àṣedòru, ó sì gbé ọtí dání. 2. Nígbà tó yá, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàìsàn, ó sì ń lọ̀ògùn. 3. Àwọn ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin ń gbádùn ara wọn níta gbangba lọ́wọ́ ìrọ̀lẹ́. Àwọn arákùnrin méjì náà ń kọrin, wọ́n ń jó, wọ́n sì ń jẹun pa pọ̀. 4. Lọ́jọ́ kejì, wọ́n lọ sóde ìwàásù.

Ó máa ń dà bíi pé àwọn tó ń lépa àwọn nǹkan ayé yìí ń gbádùn ara wọn, àmọ́ ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀. Àwọn tó ń sin Jèhófà ló máa ń ní ayọ̀ tòótọ́

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Owe 13:24—Ìkìlọ̀ wo ni Bíbélì yìí fún wa tó bá dọ̀rọ̀ bíbá ọmọ wí? (it-2 276 ¶2)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Owe 13:1-17 (th ẹ̀kọ́ 10)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ohun kan tó ṣẹlẹ̀ ládùúgbò yín bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ, lẹ́yìn náà fi ohun kan hàn án nínú Bíbélì tó máa nífẹ̀ẹ́ sí. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Pe ẹni náà wá sípàdé. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 3)

6. Àsọyé

(5 min.) lmd àfikún A kókó 9—Àkòrí: Táwọn Ọmọ Bá Ń Bọ̀wọ̀ Fáwọn Òbí Wọn Tí Wọ́n sì Jẹ́ Onígbọràn, Nǹkan Á Máa Lọ Dáadáa fún Wọn. (th ẹ̀kọ́ 16)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 77

7. “Ìmọ́lẹ̀ Àwọn Olódodo Mọ́lẹ̀ Rekete”

(8 min.) Ìjíròrò.

Ìmọ̀ àti ọgbọ́n tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kò láfiwé. Tá a bá ń fi ohun tá a kọ́ nínú ẹ̀ sílò, a máa ní ayọ̀ tòótọ́, ìgbésí ayé wa sì máa nítumọ̀. Ayé Sátánì ò lè fún wa láwọn nǹkan yìí láé.

Apá kan nínú fídíò “Ayé Yìí Ò Lè Fún Ẹ Ní Ohun Tí Kò Ní.” Arábìnrin Gainanshina jókòó sínú pápá, ó gbójú sókè, ó ń wojú ọ̀run.

Jẹ́ káwọn ará wo FÍDÍÒ Ayé Yìí Ò Lè Fún Ẹ Ní Ohun Tí Kò Ní. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Báwo ni ìrírí Arábìnrin Gainanshina ṣe jẹ́ ká rí i pé “ìmọ́lẹ̀ àwọn olódodo” dáa ju “fìtílà àwọn ẹni burúkú” lọ?—Owe 13:9

Má ṣe máa ronú nípa àwọn nǹkan tó wà nínú ayé tàbí kó o máa kábàámọ̀ àwọn ìpinnu tó o ṣe tó jẹ́ kó o lè máa ṣe iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. (1Jo 2:15-17) Kàkà bẹ́ẹ̀, ‘ìmọ̀ tó ṣeyebíye ju ohun gbogbo lọ’ tó o ní ni kó o gbájú mọ́.—Flp 3:8.

OHUN TẸ́ Ẹ LÈ ṢE NÍGBÀ ÌJỌSÌN ÌDÍLÉ:

Látìgbàdégbà, ẹ máa wo àwọn fídíò tó wà lábẹ́ ọ̀wọ́ fídíò náà Òtítọ́ Ń Yí Ìgbésí Ayé Pa Dà. Á jẹ́ kó o rí bí òtítọ́ ṣe ṣeyebíye tó.

8. Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ

(7 min.)

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 26 ¶9-17

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 43 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́