ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb25 July ojú ìwé 6-7
  • July 21-27

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • July 21-27
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
mwb25 July ojú ìwé 6-7

JULY 21-27

ÒWE 23

Orin 97 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Àwọn Ìlànà Tó Kan Ọ̀rọ̀ Ọtí Mímu

(10 min.)

Tó o bá pinnu láti mu ọtí, ṣọ́ra fún àmujù (Owe 23:20, 21; w04 12/1 19 ¶5-6)

Máa rántí ohun tí ọtí àmujù lè fà (Owe 23:29, 30, 33-35; w23.12 14 ¶4)

Má ṣe máa ronú pé ọtí ò lè ṣe ẹ́ ní nǹkan kan (Owe 23:31, 32)

Arábìnrin kan jókòó sórí àga, ó sì ń wo ìgò ọtí tó wà níwájú rẹ̀.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Owe 23:21—Kí ni ìyàtọ̀ tó wà láàárín ẹni tó jẹ́ alájẹkì àti ẹni tó sanra jọ̀kọ̀tọ̀? (w04 11/1 31 ¶2)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Owe 23:1-24 (th ẹ̀kọ́ 5)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(2 min.) ÌWÀÁSÙ NÍBI TÍ ÈRÒ PỌ̀ SÍ. (lmd ẹ̀kọ́ 3 kókó 5)

5. Pa Dà Lọ

(5 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi bá a ṣe ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì han ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 5)

6. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(5 min.) Fún akẹ́kọ̀ọ́ ẹ níṣìírí bó ṣe ń sapá láti borí ìwà kan tí kò dáa. (lmd ẹ̀kọ́ 12 kókó 4)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 35

7. Ṣé Kí N Pín Ọtí Tàbí Kí N Má Ṣe Bẹ́ẹ̀?

(8 min.) Ìjíròrò.

Ṣé ó yẹ kí ọtí wà níbi àwẹ̀jẹ-àwẹ̀mu irú bí ìgbéyàwó? Kálukú ló máa pinnu. Àmọ́ kẹ́nì kan tó ṣèpinnu, ó yẹ kó fara balẹ̀ ronú dáadáa nípa àwọn ìlànà Bíbélì kan àtàwọn nǹkan míì tó ṣe pàtàkì.

Àwọn méjì tó ń fẹ́ra sọ́nà ń ronú bóyá káwọn pín ọtí níbi ìgbéyàwó wọn. Lára ohun tó wà lórí tábìlì ni Bíbélì àti fóònù tí àwòrán ọtí wà lójú ẹ̀.

Jẹ́ káwọn ará wo FÍDÍÒ Ṣó Yẹ Kí N Fún Àwọn Èèyàn Ní Ọtí Níbi Ìgbéyàwó Mi? Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Tí ẹni tó pe àwọn èèyàn síbi àwẹ̀jẹ-àwẹ̀mu bá ronú lórí àwọn ìlànà Bíbélì yìí, báwo nìyẹn ṣe máa jẹ́ kó lè pinnu bóyá kóun pín ọtí tàbí kóun má ṣe bẹ́ẹ̀?

    • Jo 2:9—Jésù sọ omi di ọtí wáìnì níbi àsè ìgbéyàwó.

    • 1Kọ 6:10—“Àwọn ọ̀mùtípara . . . kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run.”

    • 1Kọ 10:31, 32—“Bóyá ẹ̀ ń jẹ tàbí ẹ̀ ń mu . . . , ẹ máa ṣe ohun gbogbo fún ògo Ọlọ́run. Ẹ máa ṣọ́ra kí ẹ má bàa di ohun ìkọ̀sẹ̀.”

  • Àwọn nǹkan wo ló tún yẹ kó o gbé yẹ̀ wò?

  • Tá a bá fẹ́ ṣe ìpinnu tó dáa, kí nìdí tó fi yẹ ká lo “agbára ìrònú” wa tá a bá ń gbé àwọn ìlànà Bíbélì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ yẹ̀ wò?—Ro 12:1; Onw 7:16-18

8. Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ

(7 min.)

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 2, ọ̀rọ̀ ìṣáájú fún apá 2, àti ẹ̀kọ́ 3

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 40 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́